Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 41

Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Ìbálòpọ̀?

Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Ìbálòpọ̀?

Ọ̀pọ̀ èèyàn ni kì í fẹ́ sọ̀rọ̀ nípa ìbálòpọ̀. Àmọ́ Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa ìbálòpọ̀ dáadáa, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ lọ́nà tó fọ̀wọ̀ hàn. Ohun tí Bíbélì bá sọ máa ń ṣe wá láǹfààní gan-an. Bó sì ṣe yẹ kó rí náà nìyẹn, torí pé Jèhófà ni Ẹlẹ́dàá wa. Ó mọ ohun tó dáa jù fún wa. Ó sọ bá a ṣe lè fi ìwà àti ìṣe wa múnú òun dùn àti ohun tó yẹ ká ṣe tá a bá fẹ́ gbádùn ayé wa títí láé.

1. Kí ni Jèhófà sọ nípa ìbálòpọ̀?

Ìbálòpọ̀ jẹ́ ẹ̀bùn látọ̀dọ̀ Jèhófà. Àwọn tọkọtaya sì ni Jèhófà fẹ́ kí wọ́n máa ní ìbálòpọ̀. Kì í ṣe torí ọmọ bíbí nìkan ni Jèhófà ṣe fún wọn lẹ́bùn yìí, àmọ́ ó tún jẹ́ ọ̀nà láti gbà fìfẹ́ tó jinlẹ̀ hàn sí ara wọn, kí wọ́n sì gbádùn ara wọn. Ìdí nìyẹn tí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fi sọ pé: “Máa yọ̀ pẹ̀lú aya ìgbà èwe rẹ.” (Òwe 5:18, 19) Jèhófà fẹ́ káwọn tọkọtaya Kristẹni jẹ́ olóòótọ́ sí ara wọn, ìyẹn ni kò ní jẹ́ kí wọ́n ṣe àgbèrè.​—Ka Hébérù 13:4.

2. Kí ni ìṣekúṣe?

Bíbélì sọ pé “àwọn oníṣekúṣe . . . kò ní jogún Ìjọba Ọlọ́run.” (1 Kọ́ríńtì 6:9, 10) Ọ̀rọ̀ náà por·neiʹa ni àwọn tó kọ Ìwé Mímọ́ Lédè Gíríìkì lò nígbà tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ nípa ìṣekúṣe. Lára ohun tó túmọ̀ sí ni (1) kí àwọn tí kì í ṣe tọkọtaya máa bá ara wọn lò pọ̀, a (2) kí ọkùnrin àti ọkùnrin tàbí obìnrin àti obìnrin máa bá ara wọn lò pọ̀, àti (3) kí èèyàn máa bá ẹranko lò pọ̀. Tá a bá ń “ta kété sí ìṣekúṣe,” a máa jàǹfààní púpọ̀, a sì máa múnú Jèhófà dùn.​—1 Tẹsalóníkà 4:3.

KẸ́KỌ̀Ọ́ JINLẸ̀

Jẹ́ ká wo bá a ṣe lè máa sá fún ìṣekúṣe àti àǹfààní tó o máa rí tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀.

3. Máa sá fún ìṣekúṣe

Ńṣe ni ọkùnrin olóòótọ́ náà Jósẹ́fù jà fitafita kó lè sá fún ìṣekúṣe. Ka Jẹ́nẹ́sísì 39:1-12, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Kí nìdí pàtàkì tí Jósẹ́fù fi sá fún ìṣekúṣe?​—Wo ẹsẹ 9.

  • Ṣé o rò pé ó bọ́gbọ́n mu bí Jósẹ́fù ṣe sá fún ìṣekúṣe? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?

Báwo làwọn ọ̀dọ́ ṣe lè sá fún ìṣekúṣe bíi ti Jósẹ́fù? Wo FÍDÍÒ yìí.

Jèhófà fẹ́ ká máa sá fún ìṣekúṣe. Ka 1 Kọ́ríńtì 6:18, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Àwọn nǹkan wo ló lè mú kéèyàn jìn sọ́fìn ìṣekúṣe?

  • Báwo lo ṣe lè máa sá fún ìṣekúṣe?

4. O lè borí ìdẹwò!

Kí ló lè mú kó nira láti sá fún ìṣekúṣe? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

  • Nínú fídíò yẹn, kí ni arákùnrin yẹn ṣe nígbà tó rí i pé àwọn nǹkan tí òun ń rò àtàwọn nǹkan tí òun ń ṣe lè mú kóun ṣe ìṣekúṣe?

Àwọn Kristẹni olóòótọ́ náà máa ń jà fitafita kí èrò tí kò dáa má bàa jọba lọ́kàn wọn. Kí lo lè ṣe kí èròkérò má bàa jọba lọ́kàn ẹ? Ka Fílípì 4:8, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Àwọn nǹkan wo ló yẹ ká máa ronú lé lórí?

  • Tá a bá ń ka Bíbélì tá a sì ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe lẹ́nu iṣẹ́ Jèhófà báwo nìyẹn ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ ká má bàa jìn sọ́fìn ẹ̀ṣẹ̀?

5. Àwọn ìlànà Jèhófà máa ń ṣe wá láǹfààní

Jèhófà mọ ohun tó dáa jù fún wa. Ó sọ bá a ṣe lè sá fún ìṣekúṣe àti àǹfààní tá a máa rí tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀. Ka Òwe 7:7-27 tàbí kó o wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

  • Báwo ni ọ̀dọ́kùnrin yẹn ṣe kó ara ẹ̀ síṣòro?​—Wo Òwe 7:8, 9.

  • Òwe 7:23, 26 jẹ́ ká mọ̀ pé ìṣekúṣe lè kó wa síṣòro ńlá. Tá a bá ń sá fún ìṣekúṣe, àwọn ìṣòro wo la ò ní kó sí?

  • Tá a bá ń sá fún ìṣekúṣe, báwo nìyẹn ṣe máa jẹ́ ká gbádùn ayé wa títí láé?

Bíbélì sọ pé àwọn ọkùnrin tó ń bá ọkùnrin lò pọ̀ àti àwọn obìnrin tó ń bá obìnrin lò pọ̀ kò ní jogún Ìjọba Ọlọ́run. Àwọn kan gbà pé ohun tí Bíbélì sọ yìí kò bọ́gbọ́n mu. Àmọ́, Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ wa gan-an ni, ó sì fẹ́ kí gbogbo wa máa gbádùn ayé wa títí láé. Torí náà, tá a bá fẹ́ gbádùn ayé wa títí láé, a gbọ́dọ̀ máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà ẹ̀. Ka 1 Kọ́ríńtì 6:9-11, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

  • Ṣé kí ọkùnrin máa bá ọkùnrin lò pọ̀ tàbí kí obìnrin máa bá obìnrin lò pọ̀ nìkan ni Ọlọ́run sọ pé kò dáa?

Tá a bá fẹ́ múnú Ọlọ́run dùn, gbogbo wa la gbọ́dọ̀ ṣe àwọn àyípadà kan tàbí òmíì. Kí nìdí tó fi yẹ ká máa sapá gan-an láti ṣe àwọn àyípadà náà? Ka Sáàmù 19:8, 11, kó o sì dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

  • Ṣé o rò pé àwọn ìlànà Jèhófà bọ́gbọ́n mu? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?

Jèhófà ti ran ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́wọ́ láti máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà rẹ̀. Ó lè ran ìwọ náà lọ́wọ́

ÀWỌN KAN SỌ PÉ: “Táwọn méjì bá ṣáà ti nífẹ̀ẹ́ ara wọn, kò burú tí wọ́n bá bá ara wọn lò pọ̀.”

  • Kí lèrò tìẹ?

KÓKÓ PÀTÀKÌ

Ìbálòpọ̀ jẹ́ ẹ̀bùn tí Jèhófà fún àwọn tọkọtaya kí wọ́n lè máa fi ìfẹ́ tó jinlẹ̀ hàn sí ara wọn, kí wọ́n sì máa gbádùn ara wọn.

Kí lo rí kọ́?

  • Àwọn apá wo ni àgbèrè pín sí?

  • Tá ò bá fẹ́ jìn sọ́fìn ìṣekúṣe, kí ló yẹ ká máa ṣe?

  • Tá a bá ń sá fún ìṣekúṣe bí Jèhófà ṣe sọ, àǹfààní wo ló máa ṣe wá?

Ohun tó yẹ kó o ṣe

ṢÈWÁDÌÍ

Ka ìwé yìí, kó o lè mọ̀ bóyá ó ṣe pàtàkì sí Ọlọ́run pé kí ọkùnrin àti obìnrin ṣègbéyàwó kí wọ́n tó máa gbé pọ̀.

“Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Gbígbé Pọ̀ Láìṣègbéyàwó?” (Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì)

Ka ìwé yìí kó o lè rí i pé bó tiẹ̀ jẹ́ pé Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé kí ọkùnrin àti ọkùnrin máa bá ara wọn lò pọ̀ tàbí kí obìnrin àti obìnrin máa bá ara wọn lò pọ̀ kò dáa rárá, síbẹ̀ èyí ò túmọ̀ sí pé ká kórìíra àwọn tó ń ṣe bẹ́ẹ̀.

“Ṣó Burú Kí Ọkùnrin Máa Fẹ́ Ọkùnrin àbí Kí Obìnrin Máa Fẹ́ Obìnrin?” (Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì)

Ka ìwé yìí kó o lè rí i pé ńṣe ni àwọn ìlànà Ọlọ́run nípa ìbálòpọ̀ ń dáàbò bò wá.

“Ṣé A Lè Ka Fífi Ẹnu Lá Ẹ̀yà Ìbímọ Ẹlòmíì sí Ìbálòpọ̀?” (Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì)

Ka ìtàn tí àkòrí ẹ̀ sọ pé “Wọ́n Bọ̀wọ̀ Fún Mí,” kó o lè rí ohun tó mú kí ọkùnrin kan tó máa ń bá ọkùnrin bíi tiẹ̀ lò pọ̀ ṣe àyípadà kó lè máa múnú Ọlọ́run dùn.

“Bíbélì Máa Ń Yí Ìgbésí Ayé Àwọn Èèyàn Pa Dà” (Ilé Ìṣọ́, April 1, 2011)

a Lára àwọn apá tí àgbèrè pín sí ni ìbálòpọ̀ ní tààràtà, fífi ẹnu lá ẹ̀yà ìbímọ ẹlòmíì, ìbálòpọ̀ láti ihò ìdí àti kéèyàn máa fọwọ́ pa ẹ̀yà ìbímọ ẹlòmíì.