Ìwé Ìtàn Bíbélì

Gbádùn àwọn ìtàn 116 tó wà nínú Bíbélì. Ó rọrùn láti lóyé, ó jóòótọ̀, ó sì ní àwọn àwòrán tó rẹwà.

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú

Inú Bíbélì, ìwé tó ṣe pàtàkì jù láyé, la ti mú àwọn ìtàn tó jóòótọ́ yìí. Wàá rí ìtàn ilẹ̀ ayé wa, bẹ̀rẹ̀ láti ìgbà tí Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí í dá àwọn nǹkan.

ÌTÀN 1

Ọlọ́run Bẹ̀rẹ̀ Sí í Ṣẹ̀dá Àwọn Nǹkan

Ìtàn ìṣẹ̀dá tó wà nínú Jẹ́nẹ́sísì dùn, ó sì rọrùn lóye, àní fún àwọn ọmọdé pàápàá.

ÌTÀN 2

Ọgbà Ẹlẹ́wà Kan

Gẹ́gẹ́ bí ìwé Jẹ́nẹ́sísì ṣe sọ, Ọlọ́run dá ọgbà Édẹ́nì lọ́nà tó ṣàrà ọ̀tọ̀. Ọlọ́run fẹ́ kí gbogbo ayé rẹwà bí ọgbà Édẹ́nì.

ÌTÀN 3

Ọkùnrin àti Obìnrin Àkọ́kọ́

Ọlọ́run dá Ádámù àti Éfà, ó sì fi wọ́n sínú ọgbà Édẹ́nì. Àwọn ló kọ́kọ́ ṣègbeyàwó láyé.

ÌTÀN 4

Ìdí Tí Wọ́n Fi Pàdánù Ibùgbé Wọn

Ìwé Jẹ́nẹ́sísì jẹ́ ká mọ bí párádísè àkọ́kọ́ ṣe dàwátì.

ÌTÀN 5

Ìgbésí Ayé Líle Koko Bẹ̀rẹ̀

Lẹ́yìn tí Ádámù àti Éfà kúrò ní ọgbà Édẹ́nì, wọ́n kojú oríṣiríṣi ìṣòro. Tó bá jẹ́ pé wọ́n gbọ́ ti Ọlọ́run ni, ìgbé ayé àwọn àti àwọn ọmọ wọn ì bá ládùn, ì bá sì lóyin.

ÌTÀN 6

Ọmọ Rere àti Ọmọ Búburú

Ìtàn Kéènì àti Ébẹ́lì tó wà nínú ìwé Jẹ́nẹ́sísì jẹ́ ká mọ irú ẹni tó yẹ ká jẹ́ àti àwọn ìwà tó yẹ ká yì pa dà kó tó pẹ́ jù

ÌTÀN 7

Ọkùnrin Onígboyà

Bí Énọ́kù ṣe nígboyà jẹ́ ká mọ̀ pé èèyàn lè máa ṣe ohun rere tí àwọn tó yí i ká bá tiẹ̀ ń ṣe ohun búburú.

ÌTÀN 8

Àwọn Òmìrán ní Ayé

Jẹ́nẹ́sísì orí 6 sọ nípa àwọn òmìrán tó ń ṣe àwọn èèyàn léṣe. Néfílímù ni wọ́n ń pé àwọn òmìrán yìí, àwọn ni ọmọ tí àwọn áńgẹ́lì tó fi ọ̀run sílẹ̀ wá sáyé bí.

ÌTÀN 9

Nóà Kan Ọkọ̀ Áàkì

Nóà àti ìdílé rẹ̀ la Ìkún Omi já nítorí pé wọ́n gbọ́ràn sí Ọlọ́run bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn yóòkù ò gbọ́ràn.

ÌTÀN 10

Ìkún-Omi Ńlá

Àwọn èèyàn fi Nóà ṣe yẹ̀yẹ́ nígbà tó kìlọ̀ fún wọn nípa Ìkún-Omi. Àmọ́, wọn ò rẹ́rìn-ín mọ nígbà tí òjò bẹ̀rẹ̀ sí í rọ̀. Kọ́ nípa bí ọkọ̀ áàkì tí Nóà kàn ṣe gba Nóà àti ìdílé rẹ̀ àti ọ̀pọ̀ àwọn ẹranko là.

ÌTÀN 11

Òṣùmàrè Àkọ́kọ́

Nígbà tó o bá rí òṣùmàrè, kí ló yẹ kó máa rán ẹ létí?

ÌTÀN 12

Àwọn Èèyàn Kọ́ Ilé Gogoro

Inú Ọlọ́run ò dùn sí i, ìyà tó sì fi jẹ wọ́n ṣì ń pọ́n wa lójú dòní.

ÌTÀN 13

Ábúráhámù—Ọ̀rẹ́ Ọlọ́run

Kí ló dé ti Ábúráhámù fi fi ilé rẹ̀ tó tura sílẹ̀ tó wá lọ lo gbogbo ìgbésí ayé rẹ̀ tó kù nínú àgọ́?

ÌTÀN 14

Ọlọ́run Dán Ìgbàgbọ́ Ábúráhámù Wò

Kí ló dé tí Ọlọ́run ṣe ní kí Ábúráhámù fi Ísákì ọmọ rẹ̀ rúbọ?

ÌTÀN 15

Ìyàwó Lọ́ọ̀tì Bojú Wẹ̀yìn

A lè rí ẹ̀kọ́ pàtàkì kọ́ nínú ohun tó ṣe.

ÌTÀN 16

Ísákì Rí Ìyàwó Rere Fẹ́

Kí ló mú kí Rèbékà jẹ́ ìyàwó rere? Ṣé ẹwà rẹ̀ ni àbí nǹkan míì?

ÌTÀN 17

Àwọn Ìbejì Tí Wọn Ò Jọra

Ísọ̀ ni Ísákì tó jẹ́ bàbá wọn fẹ́ràn jù, àmọ́ Jékọ́bù ni Rèbékà ìyá wọn fẹ́ràn jù ní tiẹ̀.

ÌTÀN 18

Jékọ́bù Lọ Sí Háránì

Léà ni Jékọ́bù kọ́kọ́ fẹ́ bó tiẹ̀ jẹ́ pé Rákélì gangan ló nífẹ̀ẹ́.

ÌTÀN 19

Jékọ́bù Ní Ìdílé Ńlá

Ṣé orúkọ àwọn ọmọkùnrin Jékọ́bù náà ni wọ́n fi sọ àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì méjìlá?

ÌTÀN 20

Dínà Kó Sínú Ìjàngbọ̀n

Àwọn ọ̀rẹ́ burúkú tó yàn ló fà á.

ÌTÀN 21

Àwọn Ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù Kórìíra Rẹ̀

Kí ló lè mú kí àwọn kan lára wọn fẹ́ pa àbúrò wọn?

ÌTÀN 22

Wọ́n Ju Jósẹ́fù Sẹ́wọ̀n

Kì í ṣe torí o ṣẹ̀ ni wọ́n ṣe jù ú sẹ́wọ̀n, torí pé ó ṣe ohun tó tọ́ ni.

ÌTÀN 23

Àwọn Àlá Fáráò

Ohun kan náà ni màlúù méje àti ṣírí ọkà méje náà túmọ̀ sí.

ÌTÀN 24

Jósẹ́fù Dán Àwọn Ẹ̀gbọ́n Rẹ̀ Wò

Báwo ló ṣe máa mọ̀ bóyá ìwà wọn ti yí pa dà kúrò ní bó ṣe rí nígbà tí wọ́n tà á bí ẹrú?

ÌTÀN 25

Ìdílé Náà Ṣí Lọ sí Íjíbítì

Kí ló dé tó jẹ́ pé ọmọ Ísírẹ́lì ní wọ́n ń pe ìdílé Jékọ́bù dípò kí wọ́n máa pè wọ́n ní ọmọ Jékọ́bù?

ÌTÀN 26

Jóòbù Jẹ́ Olóòótọ́ sí Ọlọ́run

Jóòbù pàdánù gbogbo ohun ìní, iṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ara rẹ̀ ò sì le mọ́. Ṣé Ọlọ́run ló ń fìyà jẹ ẹ́?

ÌTÀN 27

Ọba Búburú Kan Jẹ ní Íjíbítì

Kí ló dé tó ṣe sọ fún àwọn èèyàn rẹ̀ pé kí wọ́n pa gbogbo àwọn ọmọkùnrin Ísírẹ́lì tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ bí?

ÌTÀN 28

Bá a Ṣe Gba Mósè Ọmọ Ọwọ́ Là

Ìyá rẹ̀ wá ọgbọ́n dá sí ọ̀rọ̀ òfin tó sọ pé kí wọ́n pa gbogbo ọmọkùnrin Ísírẹ́lì tí wọ́n bá ṣẹ̀ṣẹ̀ bí.

ÌTÀN 29

Ìdí Tí Mósè Fi Sá Lọ

Mósè rò pé òun ti ṣe tán láti gba àwọn ọmọ Ísírẹ́lì là, àmọ́ ọ̀rọ̀ ò rí bẹ́ẹ̀.

ÌTÀN 30

Igbó Tí Ń Jó

Ọlọ́run lo oríṣiríṣi iṣẹ́ ìyanu láti jẹ́ kí Mósè mọ̀ pé ó ti tó àkókò fún un láti kó àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kúrò ní Íjíbítì.

ÌTÀN 31

Mósè àti Áárónì Lọ Rí Fáráò

Kí ló dé tí Fáráò ò gbọ́rọ̀ sí Mósè lẹ́nu pé kó dá àwọn Ísírẹ́lì sílẹ̀?

ÌTÀN 32

Àwọn Ìyọnu Mẹ́wàá

Ọlọ́run mú ìyọnu mẹ́wàá wá sórí Íjíbítì torí pé Fáráò ọba wọn ń ṣagídí, kò jẹ́ kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lọ.

ÌTÀN 33

Líla Òkun Pupa Kọjá

Mósè fi agbára Ọlọ́run pín Òkun Pupa sí méjì, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì rìn la ilẹ̀ gbígbẹ kọjá.

ÌTÀN 34

Irú Oúnjẹ Tuntun Kan

Oúnjẹ àrà ọ̀tọ̀ tí Ọlọ́run pèsè yìí ń rọ̀ láti ọ̀run.

ÌTÀN 35

Jèhófà Fún Wọn Ní Òfin Rẹ̀

Òfin méjì wo ló tóbi ju Òfin Mẹ́wàá lọ?

STORY 36

Ère Ọmọ Màlúù Oníwúrà

Kí ló mú kí àwọn èèyàn máa bọ ère tí wọ́n fi yẹtí ṣe?

ÌTÀN 37

Àgọ́ Kan Fún Ìjọsìn

Inú yàrá inú lọ́hùn-ún ní àpótí májẹ̀mú máa ń wà.

ÌTÀN 38

Àwọn Amí Méjìlá

Mẹ́wàá lára àwọn amí náà sọ ohun kan náà, àmọ́ ọ̀tọ̀ ni ohun tí àwọn méjì sọ. Ta ni kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbà gbọ́?

ÌTÀN 39

Ọ̀pá Áárónì Yọ Òdòdó

Báwo ni igi gbígbẹ kan ṣe lè mú òdòdó jáde, kó sì so èso ní òru ọjọ́ kan ṣoṣo?

ÌTÀN 40

Mósè Lu Àpáta

Ohun tí Mósè fẹ́ ṣẹlẹ̀ lóòótọ́, àmọ́ Mósè múnú bí Jèhófà.

ÌTÀN 41

Ejò Bàbà

Kí ló dé tí Ọlọ́run ṣe rán àwọn ejò olóró láti ṣán àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ?

ÌTÀN 42

Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Kan Sọ̀rọ̀

Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Báláámù rí ohun kan tí Báláámù ò lè rí.

ÌTÀN 43

Jóṣúà Di Aṣáájú

Kí ló dé tí wọ́n ṣe fi Jóṣúà rọ́pò Mósè, nígbà tó jẹ́ pé Mósè ṣì lágbára?

ÌTÀN 44

Ráhábù Fi Àwọn Amí Pa Mọ́

Báwo ni Ráhábù ṣe ran àwọn ọkùnrin méjì náà lọ́wọ́, kí ló sì bẹ̀ wọ́n pé kí wọ́n ṣe?

ÌTÀN 45

Bí Wọ́n Ṣe La Odò Jọ́dánì Kọjá

Iṣẹ́ ìyanu kan ṣẹlẹ̀ nígbà tí àwọn àlùfáà náà gbẹ́sẹ̀ sínú omi.

ÌTÀN 46

Odi Jẹ́ríkò

Báwo ni okùn kan lásán ṣe lè mú kí ògiri máà wó?

ÌTÀN 47

Olè Kan Ní Ísírẹ́lì

Ṣé ọkùnrin búburú kan ṣoṣo lè fa wàhálà bá gbogbo orílẹ̀-èdè?

ÌTÀN 48

Àwọn Ará Gíbéónì Ọlọgbọ́n

Wọ́n tan Jóṣúà àti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kí wọ́n lè bá wọn dá májẹ̀mú, àmọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pa àdéhùn wọn mọ́.

ÌTÀN 49

Oòrùn Dúró Sójú Kan

Jèhófà ṣe ohun kan fún Jóṣúà tí kò ṣe rí, tí kò sì tún ṣe látìgbà yẹn.

ÌTÀN 51

Rúùtù Àti Náómì

Rúùtù fi àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀ kò lè máa bá Náómì gbé, kó sì máa sin Jèhófà.

ÌTÀN 52

Gídíónì Àti Ọ̀ọ́dúnrún Ọkùnrin Rẹ̀

Ọ̀nà àrà ọ̀tọ̀ kan ni Ọlọ́run gbà yan àwọn kéréje tó máa lọ sí ojú ogun, bí wọn ṣe mu omi ló lò.

ÌTÀN 53

Ìlérí Jẹ́fútà

Kì í ṣe òun nìkan ni ìlérí tó ṣe fún Jèhófà kàn, ó tún kan ọmọbìnrin rẹ̀.

ÌTÀN 54

Ọkùnrin Tó Lágbára Jù Lọ

Báwo ni Dèlílà ṣe mọ àṣírí agbára Sámúsìnì?

ÌTÀN 55

Ọmọkùnrin Kékeré Kan Sin Ọlọ́run

Ọlọ́run rán Sámúẹ́lì ní iṣẹ́ kan tó le sí Élì, Wòlíì Àgbà.

ÌTÀN 56

Sọ́ọ̀lù—Ọba Àkọ́kọ́ Ní Ísírẹ́lì

Ọlọ́run ló yan Sọ́ọ̀lù ní ìbẹ̀rẹ̀, àmọ́ ó kọ̀ ọ́ nígbà tó yá. A lè kọ́ ẹ̀kọ́ pàtàkì látinú ọ̀rọ̀ Sọ́ọ̀lù.

ÌTÀN 57

Ọlọ́run Yan Dáfídì

Kí ni Ọlọ́run rí lára Dáfídì tí wòlíì Sámúẹ́lì ò rí?

ÌTÀN 58

Dáfídì àti Gòláyátì

Kì í ṣe kànnàkànnà nìkan ni Dáfídì fi bá Gòláyátì jà, agbára ńlá kan ló lò.

ÌTÀN 59

Ìdí Tí Dáfídì Fi Gbọ́dọ̀ Sá Lọ

Inú Sọ́ọ̀lù kọ́kọ́ dùn sí Dáfídì, àmọ́ nígbà tó yá ó bẹ̀rẹ̀ sí í jowú Sọ́ọ̀lù débi pé ó fẹ́ pa á. Kí ló dé?

ÌTÀN 60

Ábígẹ́lì àti Dáfídì

Ábígẹ́lì pe ọkọ rẹ̀ ní aláìmọ̀kan, àmọ́ ìyẹn ni kò jẹ́ kí wọ́n gbẹ̀míí ọkọ rẹ̀ lọ́jọ́ náà.

ÌTÀN 61

Wọ́n Fi Dáfídì Jọba

Àwọn ohun tí Dáfídì ṣe àti àwọn ohun tí kò ṣe fi hàn pé ó kúnjú ìwọ̀n láti di ọba Ísírẹ́lì.

ÌTÀN 62

Wàhálà Nínú Ilé Dáfídì

Àṣìṣe kan ṣoṣo péré ni Dáfídì ṣe tó fi kó wàhálà bá òun àti ìdílé rẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún.

ÌTÀN 63

Ọlọ́gbọ́n Ọba Sólómọ́nì

Ṣé Sólómọ́nì máa gé ọmọ ìkókó yìí sí méjì lóòótọ́?

ÌTÀN 64

Sólómọ́nì Kọ́ Tẹ́ńpìlì

Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ọlọ́gbọ́n ní Sólómọ́nì, wọ́n tì í ṣe ohun tí kò mọ́gbọ́n dání, tó sì burú.

ÌTÀN 65

Ìjọba Náà Pín sí Méjì

Gbàrà tí Jèróbóámù bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ló ti mú kí àwọn èèyàn náà máa rú òfin Ọlọ́run.

ÌTÀN 66

Jésíbẹ́lì—Ayaba Búburú

Kò sí nǹkan tí kò ní ṣe kí ọwọ́ rẹ̀ lè tẹ ohunkóhun tó bá fẹ́.

ÌTÀN 67

Jèhóṣáfátì Gbẹ́kẹ̀ Lé Jèhófà

Kí ló dé tó ṣe jẹ́ pé àwọn akọrin tí kò ní ohun ìjà kankan ló ṣáájú àwọn ọmọ ogun lọ sójú ogun?

ÌTÀN 68

Àwọn Ọmọkùnrin Méjì Tó Jí Dìde

Ṣé ẹni tó ti kú lé jíǹde? Ó ti ṣẹlẹ̀ rí!

ÌTÀN 69

Ọmọbìnrin Kan Ran Ọkùnrin Alágbára Kan Lọ́wọ́

Ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀, ìyẹn sì mú kí iṣẹ́ ìyanu kan ṣẹlẹ̀.

ÌTÀN 70

Jónà àti Ẹja Ńlá Náà

Jónà kọ́ ẹ̀kọ́ pàtàkì, pé kí èèyàn máa ṣe ohun tí Jèhófà bá sọ.

ÌTÀN 71

Ọlọ́run Ṣèlérí Párádísè

Párádisè àkọ́kọ́ kéré, èyí tó ń bọ̀ yìí máa bo gbogbo ayé.

ÌTÀN 72

Ọlọ́run Ran Hesekáyà Ọba Lọ́wọ́

Ní òrú ọjọ́ kan, áńgẹ́lì kan pa 185,000 ọmọ ogun Ásíríà.

ÌTÀN 73

Ọba Rere Tó Jẹ Kẹ́yìn ní Ísírẹ́lì

Jòsáyà kò tíì pé ọmọ ogun ọdún nígbà tó ṣe nǹkan kan tó gba ìgboyà.

ÌTÀN 73

Ọba Rere Tó Jẹ Kẹ́yìn ní Ísírẹ́lì

Jòsáyà kò tíì pé ọmọ ogun ọdún nígbà tó ṣe nǹkan kan tó gba ìgboyà.

ÌTÀN 75

Ọmọkùnrin Mẹ́rin Ní Bábílónì

Wọ́n ṣe ohun tó tọ́ bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n kó wọn kúrò lọ́dọ̀ àwọn òbí wọn.

ÌTÀN 76

Wọ́n Pa Jerúsálẹ́mù Run

Kí ló dé tí Ọlọ́run ṣe jẹ́ kí àwọn ará Bábílónì tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá Ísírẹ́lì pa Jerúsálẹ́mù run?

ÌTÀN 77

Wọ́n Kọ̀ Láti Tẹrí Ba

Ṣé Ọlọ́run máa gba àwọn ọkùnrin olóòótọ́ mẹ́ta yìí nínú iná tó ń jó?

ÌTÀN 78

Ìkọ̀wé Lára Ògiri

Wòlíì Dáníẹ́lì túmọ̀ ọ̀rọ̀ mẹ́rin kan tó jẹ́ àdììtú.

ÌTÀN 79

Dáníẹ́lì Nínú Ihò Kìnnìún

Dáníẹ́lì gba ìdájọ́ ikú, àmọ́ ṣé ó ní ohun tó lè ṣe tí kò fi ní kú?

ÌTÀN 80

Àwọn Èèyàn Ọlọ́run Kúrò Ní Bábílónì

Nígbà tí Ọba Kírúsì ṣẹ́gun ìlú Bábílónì, ó mú àsọtẹ́lẹ̀ kan ṣẹ, ó tún mú òmíràn ṣẹ báyìí.

ÌTÀN 81

Gbígbẹ́kẹ̀lé Ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run

Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rú òfin èèyàn kí wọ́n lè ṣègbọràn sí Ọlọ́run. Ṣé Ọlọ́run á bù kún wọn?

ÌTÀN 82

Módékáì àti Ẹ́sítérì

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Ayaba Fáṣítì rẹwà, kí ló dé tí Ọba Ahasuwérúsì fi fi Ẹ́sítérì rọ́pò rẹ̀ bí ayaba?

ÌTÀN 83

Odi Jerúsálẹ́mù

Níbi tí wọ́n ti ń tún ògiri náà kọ́, àfi kí àwọn òṣìṣẹ́ náà máa mú idà àti ọ̀kọ̀ dání tọ̀sántòru.

ÌTÀN 84

Áńgẹ́lì Kan Bẹ Màríà Wò

Ó wá jíṣẹ́ kan fún Màríà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run pé ó máa bí ọmọ kan tó máa jẹ́ ọba títí láé..

ÌTÀN 86

Àwọn Ọkùnrin Tí Ìràwọ̀ Kan Darí

Ta ló darí àwọn amòye náà sọ́dọ̀ Jésù? Ìdáhùn náà lè yà ọ́ lẹ́nu.

ÌTÀN 87

Jésù Ọ̀dọ́mọdé Nínú Tẹ́ńpìlì

Ó ní ohun kan tó ya àwọn àgbà ọkùnrin tó ń kọ́ni ní tẹ́ńpìlì pàápàá lẹ́nu.

ÌTÀN 88

Jòhánù Batisí Jésù

Jòhánù ti máa ń ri àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bọmi, àmọ́ nígbà tí Jésù kò dẹ́ṣẹ̀ rí, kí ló dé tí Jòhánù fi rì í bọmi?

ÌTÀN 89

Jésù Fọ Tẹ́ńpìlì Mọ́

Ìfẹ́ tí Jésù ní ló mú kó bínú.

ÌTÀN 90

Pẹ̀lú Obìnrin Kan Lẹ́bàá Kànga

Báwo ni omi tí Jésù ṣe fẹ́ fún un á ṣe jẹ́ kí òùngbẹ má gbẹ ẹ́ mọ́ láé?

ÌTÀN 91

Jésù Kọ́ Àwọn Èèyàn Lórí Òkè

Kọ́ nípa àwọn ọ̀rọ̀ ọgbọ́n tó máa ń wúlò ní gbogbo ìgbà tó wà nínú Ìwáású Orí Òkè.

ÌTÀN 92

Jésù Jí Òkú Dìde

Ọ̀rọ̀ méjì péré ni Jésù sọ tó fi fi agbára Ọlọ́run jí ọmọbìnrin Jáírù dìde.

ÌTÀN 93

Jésù Bọ́ Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Èèyàn

Ẹ̀kọ́ pàtàkì wo ni iṣẹ́ ìyanu tí Jésù fi bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn kọ́ wa?

ÌTÀN 94

Jésù Fẹ́ràn Àwọn Ọmọdé

Jésù kọ́ àwọn àpọ́sítélì pé kì í ṣe pé kí wọ́n máa wo bí àwọn ọmọdé ṣe ń ṣe nìkan ní, àmọ́ kí wọ́n tún máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ wọn kí wọ́n lè kẹ́kọ̀ọ́ lára wọn dáadáa.

ÌTÀN 95

Ọ̀nà Tí Jésù Gbà Ń Kọ́ni

Jésù sábà máa ń lo irú àkàwé bíi ti ará Samáríà tó jẹ́ aláàánú yìí láti kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́.

ÌTÀN 96

Jésù Wo Àwọn Aláìsàn Sàn

Kí ni gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe jẹ́ ká mọ̀?

ÌTÀN 97

Jésù Dé Gẹ́gẹ́ Bí Ọba

Ọ̀pọ̀ èèyàn ló kí i káàbọ̀, àmọ́ kì í ṣe gbogbo èèyàn ni inú wọn dùn nípa rẹ̀.

ÌTÀN 98

Lórí Òkè Ólífì

Jésù sọ fún àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ mẹ́rin nípa àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ní àsìkò tá a wà yìí.

ÌTÀN 99

Nínú Yàrá Kan Lórí Òkè Pẹ̀tẹ́ẹ̀sì

Kí ló dé tí Jésù fi sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ láti máa jẹ oúnjẹ pàtàkì yìí lọ́dọọdún?

ÌTÀN 100

Jésù Nínú Ọgbà

Kí ló dé tí Júdásì fi fi ìfẹnukonu da Jésù?

ÌTÀN 101

Wọ́n Pa Jésù

Nígbà tó ń kú lọ lórí òpó igi oró, o ṣèlérí párádísè.

ÌTÀN 102

Jésù Jíǹde

Lẹ́yìn ti áńgẹ́lì kan yí òkúta kúrò ní ibojì Jésù, ohun tí àwọn ẹ̀ṣọ́ tó ń ṣọ́ ibẹ̀ rí yà wọ́n lẹ́nu gan-an.

STORY 103

Jésù Wọnú Yàrá Kan Tí Wọ́n Tì Pa

Kí ló dé tí àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù kò dá a mọ̀ lẹ́yìn tó jíǹde?

ÌTÀN 104

Jésù Pa Dà Sọ́run

Kí Jésù tó pa dà sọ́run, ó fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ní àṣẹ pàtàkì kan.

ÌTÀN 105

Àwọn Ọmọlẹ́yìn Dúró Sí Jerúsálẹ́mù

Kí ló dé tí Jésù tú ẹ̀mí mímọ́ jáde sórí àwọn ọmọ ẹ̀yìn ní Pẹ́ntíkọ́sì?

ÌTÀN 106

Ìdáǹdè Kúrò Nínú Túbú

Àwọn aṣáájú ìsìn Júù fi àwọn ápọ́sítélì sẹ́wọ̀n kí wọ́n má bàa wàásù mọ́, àmọ́ Ọlọ́run ní ohun míì lọ́kàn tó fẹ́ ṣe.

ÌTÀN 107

Wọ́n Sọ Sítéfánù Lókùúta Pa

Nígbà tí wọ́n ń pa Sítéfánù, ó gba àdúrà kan tó ṣàrà ọ̀tọ̀.

ÌTÀN 108

Lójú Ọ̀nà Damásíkù

Iná tó ń fọ́ni lójú àti ohùn kan tó dún láti ọ̀run yí ìgbésí ayé Sọ́ọ̀lù pa dà.

ÌTÀN 109

Pétérù Lọ Sọ́dọ̀ Kọ̀nílíù

Ṣé Ọlọ́run ka ẹ̀yà tàbí orílẹ̀-èdè kan sí ju òmíràn lọ?

ÌTÀN 110

Tímótì—Olùrànlọ́wọ́ Tuntun fún Pọ́ọ̀lù

Tímótì fi àwọn ẹbí rẹ̀ sílẹ̀ kó lè lọ máa wàásù pẹ̀lú Pọ́ọ̀lù.

ÌTÀN 111

Ọmọkùnrin Kan Tó Sùn Lọ

Yútíkọ́sì sùn lọ nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń sọ àsọyé àkọ́kọ́, àmọ́ kò sùn lọ nígbà àsọyé kejì. Iṣẹ́ ìyanu ńlá kan ṣẹlẹ̀ láàárín àsọyé méjèèjì.

ÌTÀN 112

Ọkọ̀ Rì Ní Erékùṣù Kan

Nígbà tó dà bíi pé kò sí ìrètí kankan mọ́, Ọlọ́run ránṣẹ́ sí Pọ́ọ̀lù pé ìrètí ṣì wà.

ÌTÀN 113

Pọ́ọ̀lù Ní Róòmù

Báwo ni àpọ́sítélì ṣe máa ṣe iṣẹ́ rẹ̀ g̣ẹ́gẹ́ bí àpọ́sítélì nígbà tó ń ṣẹ̀wọ̀n lọ́wọ́?

ÌTÀN 114

Òpin Gbogbo Ìwà Búburú

Kí ló dé tí Ọlọ́run ṣe rán àwọn ọmọ ogun, tí Jésù ṣáájú wọn, lọ sí ogun Amágẹ́dọ́nì?

ÌTÀN 115

Párádísè Tuntun Lórí Ilẹ̀ Ayé

Àwọn èèyàn ti gbé nínú Párádísè rí ní ayé, ó sì tún máa ṣẹlẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.

ÌTÀN 116

Bá A Ṣe Lè Wà Láàyè Títí Láé

Ṣé ká kàn mọ Jèhófà àti Jésù nìkan ti tó? Kí ló yẹ ká tún ṣe?

Àwọn Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Ìtàn Bíbélì

Àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ àti àwọn ìbéèrè fún ìkẹ́kọ̀ọ́ táá jẹ́ kí àwọn ọmọdé rí ẹ̀kọ́ kọ́ nínú ìtàn Bíbélì kọ̀ọ̀kan.