APÁ 5
Láti Ìgbà Ìkólẹ́rúlọ-sí-Bábílónì Títí Di Àkókò Títún Odi Jerúsálẹ́mù Kọ́
Nígbà táwọn ọmọ Ísírẹ́lì wà ní ìgbèkùn, ọ̀pọ̀ nǹkan ló dán ìgbàgbọ́ wọn wò. Ọba Bábílónì pàṣẹ pé kí wọ́n ju Ṣádírákì, Méṣákì àti Àbẹ́dínígò sínú iná ìléru, àmọ́ Ọlọ́run mú wọn jáde láàyè. Lẹ́yìn ìyẹn, àwọn ará Mídíà àti Páṣíà ṣẹ́gun Bábílónì, wọ́n sì ju Dáníẹ́lì sínú ihò kìnnìún, àmọ́ Ọlọ́run tún dáàbò bò ó nípa pípa àwọn kìnnìún lẹ́nu mọ́.
Níkẹyìn, Kírúsì ọba Páṣíà dá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nídè. Wọ́n padà sí ìlú wọn lẹ́yìn àádọ́rin [70] ọdún géérégé táwọn ará Bábílónì ti kó wọn nígbèkùn. Ọ̀kan lára ohun tí wọ́n kọ́kọ́ ṣe nígbà tí wọ́n padà sí Jerúsálẹ́mù ni pé wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ tẹ́ńpìlì Jèhófà. Àmọ́, kò pẹ́ káwọn ọ̀tá tó dá wọn dúró lẹ́nu iṣẹ́. Nítorí náà, ní nǹkan bí ọdún méjìlélógún [22] lẹ́yìn tí wọ́n dé Jerúsálẹ́mù ni wọ́n tó kọ́ tẹ́ńpìlì náà parí pátápátá.
Síwájú sí i, a kọ́ nípa ìrìn àjò Ẹ́sírà lọ sí ìlú Jerúsálẹ́mù láti ṣe tẹ́ńpìlì náà lọ́ṣọ̀ọ́. Èyí jẹ́ ní nǹkan bí ọdún mẹ́tàdínláàádọ́ta [47] lẹ́yìn tí wọ́n ti kọ́ tẹ́ńpìlì náà parí. Nígbà tó sì di ọdún mẹ́tàlá lẹ́yìn ìrìn àjò Ẹ́sírà, Nehemáyà ṣèrànwọ́ láti tún odi Jerúsálẹ́mù tó ti wó lulẹ̀ kọ́. Apá KARÙN-ÚN yìí kárí ìtàn ohun tó wáyé láàárín ọdún méjìléláàádọ́jọ [152] títí di àkókó tá a wà yìí.
NÍ APÁ YÌÍ
ÌTÀN 79
Dáníẹ́lì Nínú Ihò Kìnnìún
Dáníẹ́lì gba ìdájọ́ ikú, àmọ́ ṣé ó ní ohun tó lè ṣe tí kò fi ní kú?
ÌTÀN 80
Àwọn Èèyàn Ọlọ́run Kúrò Ní Bábílónì
Nígbà tí Ọba Kírúsì ṣẹ́gun ìlú Bábílónì, ó mú àsọtẹ́lẹ̀ kan ṣẹ, ó tún mú òmíràn ṣẹ báyìí.
ÌTÀN 81
Gbígbẹ́kẹ̀lé Ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run
Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rú òfin èèyàn kí wọ́n lè ṣègbọràn sí Ọlọ́run. Ṣé Ọlọ́run á bù kún wọn?
ÌTÀN 82
Módékáì àti Ẹ́sítérì
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Ayaba Fáṣítì rẹwà, kí ló dé tí Ọba Ahasuwérúsì fi fi Ẹ́sítérì rọ́pò rẹ̀ bí ayaba?
ÌTÀN 83
Odi Jerúsálẹ́mù
Níbi tí wọ́n ti ń tún ògiri náà kọ́, àfi kí àwọn òṣìṣẹ́ náà máa mú idà àti ọ̀kọ̀ dání tọ̀sántòru.