Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 69

Ṣé Ábúráhámù Ni Bàbá Wọn Àbí Èṣù?

Ṣé Ábúráhámù Ni Bàbá Wọn Àbí Èṣù?

JÒHÁNÙ 8:37-59

  • ÀWỌN JÚÙ SỌ PÉ ÁBÚRÁHÁMÙ NI BÀBÁ WỌN

  • JÉSÙ TI WÀ ṢÁÁJÚ ÁBÚRÁHÁMÙ

Jerúsálẹ́mù ni Jésù ṣì wà fún Àjọyọ̀ Àwọn Àgọ́ Ìjọsìn (tàbí Àjọyọ̀ Àtíbàbà), ó sì ń kọ́ àwọn èèyàn láwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì tó yẹ kí wọ́n mọ̀. Àwọn Júù kan tó wà lọ́dọ̀ ẹ̀ sọ fún un pé: “Ọmọ Ábúráhámù ni wá, a ò sì ṣe ẹrú ẹnikẹ́ni rí.” Jésù sọ pé: “Mo mọ̀ pé ọmọ Ábúráhámù ni yín. Àmọ́ ẹ̀ ń wá bí ẹ ṣe máa pa mí, torí pé ọ̀rọ̀ mi ò ṣe yín láǹfààní kankan. Mò ń sọ àwọn ohun tí mo ti rí nígbà tí mo wà lọ́dọ̀ Baba mi, àmọ́ ohun tí ẹ̀yin gbọ́ látọ̀dọ̀ bàbá yín lẹ̀ ń ṣe.”—Jòhánù 8:33, 37, 38.

Ohun tí Jésù ń sọ ṣe kedere, ìyẹn ni pé Baba òun yàtọ̀ sí tiwọn. Àmọ́ torí pé àwọn Júù ò lóye ohun tí Jésù ń sọ, wọ́n tún sọ ohun kan náà fún un pé: “Ábúráhámù ni bàbá wa.” (Jòhánù 8:39; Àìsáyà 41:8) Òun ni baba ńlá wọn nípa tara, torí náà wọ́n rò pé Ọlọ́run tí Ábúráhámù sìn làwọn náà ń sìn.

Àmọ́ èsì tí Jésù fún wọn yà wọ́n lẹ́nu, ó ní: “Tó bá jẹ́ pé ọmọ Ábúráhámù ni yín, àwọn iṣẹ́ Ábúráhámù lẹ̀ bá máa ṣe.” Òótọ́ sì ni torí ẹni bíni làá jọ. Jésù tún sọ pé: “Àmọ́ ní báyìí, ẹ̀ ń wá bí ẹ ṣe máa pa mí, èmi tí mo sọ òtítọ́ tí mo gbọ́ látọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún yín. Ábúráhámù ò ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀.” Jésù wá sọ ọ̀rọ̀ kan tó rú wọn lójú, ó ní: “Àwọn iṣẹ́ bàbá yín lẹ̀ ń ṣe.”—Jòhánù 8:39-41.

Síbẹ̀, àwọn Júù ò tíì mọ ẹni tí Jésù ń pè ní bàbá wọn. Wọ́n gbà pé ọmọ Ábúráhámù làwọn, wọ́n ní: “Ìṣekúṣe kọ́ ni wọ́n fi bí wa; Baba kan la ní, Ọlọ́run ni.” Àmọ́, ìbéèrè náà ni pé, ṣé Ọlọ́run ni Bàbá wọn lóòótọ́? Jésù sọ pé: “Tó bá jẹ́ Ọlọ́run ni Baba yín, ẹ máa nífẹ̀ẹ́ mi, torí pé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni mo ti wá, mo sì wà níbí. Èmi kọ́ ni mo rán ara mi wá, àmọ́ Ẹni yẹn ló rán mi.” Ó wá béèrè ìbéèrè kan tó dáhùn fúnra rẹ̀, ó ní: “Kí ló dé tí ohun tí mò ń sọ ò yé yín? Torí pé ẹ ò lè fetí sí ọ̀rọ̀ mi.”—Jòhánù 8:41-43.

Jésù ti jẹ́ kí wọ́n mọ ohun tó máa yọrí sí tí wọn ò bá gba òun gbọ́. Torí náà, ó sọ òkodoro ọ̀rọ̀ fún wọn, kò sì fọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n sọ, ó ní: “Ọ̀dọ̀ Èṣù bàbá yín lẹ ti wá, ẹ sì fẹ́ ṣe àwọn ìfẹ́ ọkàn bàbá yín.” Irú èèyàn wo ni bàbá wọn yìí? Jésù sọ irú ẹni tó jẹ́ gan-an, ó ní: “Apààyàn ni ẹni yẹn nígbà tó bẹ̀rẹ̀, kò sì dúró ṣinṣin nínú òtítọ́.” Ó tún sọ pé: “Ẹni tó bá wá látọ̀dọ̀ Ọlọ́run máa ń fetí sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Ìdí nìyí tí ẹ ò fi fetí sílẹ̀, torí pé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kọ́ lẹ ti wá.”—Jòhánù 8:44, 47.

Ohun tí Jésù sọ yẹn ká wọn lára gan-an, ni wọ́n bá sọ fún un pé: “Ṣebí a ti sọ pé, ‘Ará Samáríà ni ọ́, ẹlẹ́mìí èṣù sì ni ọ́’?” Ṣe ni wọ́n kan Jésù lábùkù bí wọ́n ṣe pè é ní “ará Samáríà.” Àmọ́ Jésù ò jẹ́ kíyẹn bí òun nínú, dípò bẹ́ẹ̀ ohun tó sọ ni pé: “Mi ò ní ẹ̀mí èṣù, àmọ́ mò ń bọlá fún Baba mi, ẹ̀yin sì ń kàn mí lábùkù.” Kàwọn èèyàn náà lè rí bí ọ̀rọ̀ Jésù ti ṣe pàtàkì tó, ó ṣèlérí pé: “Tí ẹnikẹ́ni bá ń tẹ̀ lé ọ̀rọ̀ mi, kò ní rí ikú láé.” Jésù ò sọ pé àwọn àpọ́sítélì àtàwọn tó ń tẹ̀ lé òun ò ní kú rárá. Kàkà bẹ́ẹ̀, ohun tó ń sọ ni pé wọn ò ní sí lára àwọn tó máa gba ìdájọ́ ìparun ayérayé tó túmọ̀ sí “ikú kejì,” ìyẹn àwọn tí kò nírètí pé Ọlọ́run máa jí àwọn dìde.—Jòhánù 8:48-51; Ìfihàn 21:8.

Àmọ́ àwọn Júù rò pé ikú táwọn èèyàn ń kú ni Jésù ń sọ, wọ́n wá sọ pé: “A ti wá mọ̀ báyìí pé ẹlẹ́mìí èṣù ni ọ́. Ábúráhámù kú, àwọn wòlíì náà kú, àmọ́ ìwọ sọ pé, ‘Tí ẹnikẹ́ni bá ń tẹ̀ lé ọ̀rọ̀ mi, kò ní tọ́ ikú wò láé.’ O ò tóbi ju Ábúráhámù bàbá wa tó kú lọ, àbí o tóbi jù ú lọ? . . . Ta lò ń fi ara rẹ pè?”—Jòhánù 8:52, 53.

Ó ṣe kedere pé Jésù fẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé òun ni Mèsáyà. Àmọ́ dípò kó dá wọn lóhùn ní tààràtà, ó ní: “Tí mo bá ń ṣe ara mi lógo, ògo mi ò já mọ́ nǹkan kan. Baba mi ló ń ṣe mí lógo, ẹni tí ẹ sọ pé ó jẹ́ Ọlọ́run yín. Síbẹ̀, ẹ ò tíì mọ̀ ọ́n, àmọ́ èmi mọ̀ ọ́n. Tí mo bá sì sọ pé mi ò mọ̀ ọ́n, ṣe ni màá dà bíi yín, ẹ̀yin òpùrọ́.”—Jòhánù 8:54, 55.

Lẹ́yìn náà, Jésù wá sọ̀rọ̀ nípa baba ńlá wọn tó jẹ́ olóòótọ́, ó ní: “Ábúráhámù bàbá yín yọ̀ gidigidi bó ṣe ń retí láti rí ọjọ́ mi, ó rí i, ó sì yọ̀.” Òótọ́ sì ni, torí pé Ábúráhámù gba ìlérí Ọlọ́run gbọ́, ìyẹn mú kó máa fojú sọ́nà fún ìgbà tí Mèsáyà máa dé. Àmọ́ torí pé ohun tí Jésù sọ ò nítumọ̀ sí wọn, wọ́n sọ fún un pé: “O ò tíì tó ẹni àádọ́ta (50) ọdún, síbẹ̀ o ti rí Ábúráhámù, àbí?” Jésù dá wọn lóhùn pé: “Lóòótọ́-lóòótọ́ ni mo sọ fún yín, kí Ábúráhámù tó wà, èmi ti wà.” Ìgbà tí Jésù jẹ́ áńgẹ́lì alágbára lọ́run ni Jésù ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.—Jòhánù 8:56-58.

Bí Jésù ṣe sọ pé òun ti wà ṣáájú Ábúráhámù bí àwọn Júù náà nínú, torí náà wọ́n fẹ́ sọ ọ́ lókùúta. Àmọ́ Jésù fi ibẹ̀ sílẹ̀ láìfarapa.