Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 108

Ìdáhùn Jésù Ò Jẹ́ Káwọn Ọ̀tá Rẹ̀ Rí I Mú

Ìdáhùn Jésù Ò Jẹ́ Káwọn Ọ̀tá Rẹ̀ Rí I Mú

MÁTÍÙ 22:15-40 MÁÀKÙ 12:13-34 LÚÙKÙ 20:20-40

  • OHUN TI KÉSÁRÌ PA DÀ FÚN KÉSÁRÌ

  • ṢÉ ÀWỌN ÈÈYÀN MÁA GBÉYÀWÓ NÍGBÀ ÀJÍǸDE?

  • ÀṢẸ TÓ TÓBI JÙ LỌ

Inú ń bí àwọn aṣáájú ìsìn sí Jésù, torí pé ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ àpèjúwe tó fi tú àṣírí wọn pé ìkà ni wọ́n. Làwọn Farisí bá ń wá bí wọ́n ṣe máa mú un. Wọ́n fẹ́ kó sọ ohun kan kí wọ́n lè fẹ̀sùn kàn án, kí wọ́n sì mú un lọ sọ́dọ̀ gómìnà àwọn ará Róòmù. Wọ́n tún fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn wọn lówó kí wọ́n lè bá wọn mú un.—Lúùkù 6:7.

Àwọn Farisí wá sọ pé: “Olùkọ́, a mọ̀ pé o máa ń sọ̀rọ̀, o sì máa ń kọ́ni lọ́nà tó tọ́, o kì í ṣe ojúsàájú rárá, àmọ́ ò ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run ní ìbámu pẹ̀lú òtítọ́: Ṣé ó bófin mu fún wa láti san owó orí fún Késárì àbí kò bófin mu?” (Lúùkù 20:21, 22) Jésù ò jẹ́ kí wọ́n fi ọ̀rọ̀ dídùn tan òun jẹ, torí ó mọ̀ pé alágàbàgebè àti alárèékérekè ni wọ́n. Tó bá sọ pé, ‘Rárá, kò yẹ kí wọ́n máa san owó orí yìí,’ wọ́n lè fẹ̀sùn kàn án pé ó ń dìtẹ̀ sí ìjọba Róòmù. Tó bá sì sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, ó yẹ kẹ́ ẹ máa san owó orí,’ wọ́n lè ṣi Jésù lóye torí pé ará ń kan wọ́n bí wọ́n ṣe wà lábẹ́ ìjọba Róòmù, ìyẹn sì lè mú káwọn èèyàn kẹ̀yìn sí i. Báwo ni Jésù ṣe dáhùn ìbéèrè yẹn?

Jésù fèsì pé: “Ẹ̀yin alágàbàgebè, kí ló dé tí ẹ̀ ń dán mi wò? Ẹ fi ẹyọ owó tí ẹ fi ń san owó orí hàn mí.” Wọ́n fún un ní owó dínárì, ó wá bi wọ́n pé: “Àwòrán àti àkọlé ta nìyí?” Wọ́n sọ pé: “Ti Késárì ni.” Jésù wá fún wọn ní ìtọ́ni kan, ó ní: “Torí náà, ẹ san àwọn ohun ti Késárì pa dà fún Késárì, àmọ́ ẹ fi àwọn ohun ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”—Mátíù 22:18-21.

Èsì tí Jésù fún àwọn ọkùnrin yìí yà wọ́n lẹ́nu. Bí Jésù ṣe fọgbọ́n dá wọn lóhùn yìí ò jẹ́ kí wọ́n rí ọ̀rọ̀ sọ mọ́, ni wọ́n bá kúrò níbẹ̀. Àmọ́ kàkà kí ọ̀rọ̀ náà tán lára wọn, ṣe ló túbọ̀ ń le sí i, ìsapá wọn láti mú Jésù ò tíì tán. Lẹ́yìn tí ìsapá àwọn Farisí láti mú Jésù já sí pàbó, àwọn aṣáájú ìsìn míì tún kóra jọ, wọ́n sì lọ bá a.

Àwọn Sadusí gbà pé kò sí àjíǹde, wọ́n wá lọ bá Jésù, wọ́n sì bi í ní ìbéèrè nípa àjíǹde àti ṣíṣú obìnrin lópó, wọ́n ní: “Olùkọ́, Mósè sọ pé: ‘Tí ọkùnrin èyíkéyìí bá kú láìní ọmọ, kí arákùnrin rẹ̀ fẹ́ ìyàwó rẹ̀, kó sì bímọ fún arákùnrin rẹ̀.’ Ó ṣẹlẹ̀ pé arákùnrin méje wà pẹ̀lú wa. Ẹni àkọ́kọ́ fẹ́ ìyàwó, ó sì kú, ó fi ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ fún arákùnrin rẹ̀, nígbà tó jẹ́ pé kò bí ọmọ kankan. Ohun kan náà ló ṣẹlẹ̀ sí ẹnì kejì àti ẹnì kẹta, títí dórí ẹnì keje. Nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, obìnrin náà kú. Tí àwọn méjèèje bá wá jíǹde, èwo nínú wọn ló máa fẹ́? Torí gbogbo wọn ni wọ́n ti fi ṣe aya.”—Mátíù 22:24-28.

Jésù mọ̀ pé àwọn Sadusí yẹn gba ọ̀rọ̀ Mósè gbọ́, torí náà ibẹ̀ ló ti fa ọ̀rọ̀ ẹ̀ yọ. Ó dá wọn lóhùn pé: “Ṣebí ìdí tí ẹ fi ṣàṣìṣe nìyẹn, torí pé ẹ ò mọ Ìwé Mímọ́, ẹ ò sì mọ agbára Ọlọ́run? Torí tí wọ́n bá jíǹde, àwọn ọkùnrin kì í gbéyàwó, a kì í sì í fa àwọn obìnrin fún ọkọ, àmọ́ wọ́n máa dà bí àwọn áńgẹ́lì ní ọ̀run. Àmọ́ ní ti àjíǹde àwọn òkú, ṣé ẹ ò tíì kà á nínú ìwé Mósè ni, nínú ìtàn igi ẹlẹ́gùn-ún, pé Ọlọ́run sọ fún un pé: ‘Èmi ni Ọlọ́run Ábúráhámù, Ọlọ́run Ísákì àti Ọlọ́run Jékọ́bù’? Kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, àmọ́ ó jẹ́ Ọlọ́run àwọn alààyè. Ẹ mà ṣàṣìṣe o.” (Máàkù 12:24-27; Ẹ́kísódù 3:1-6) Èsì tí Jésù fún wọn yìí ya gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ lẹ́nu gan-an.

Jésù ti pa àwọn Farisí àtàwọn Sadusí lẹ́nu mọ́, ni gbogbo wọn bá gbìmọ̀ pọ̀ láti túbọ̀ dán an wò. Ọ̀kan lára àwọn akọ̀wé òfin wá bi í pé: “Olùkọ́, àṣẹ wo ló tóbi jù lọ nínú Òfin?”—Mátíù 22:36.

Jésù fèsì pé: “Àkọ́kọ́ ni, ‘Gbọ́, ìwọ Ísírẹ́lì, Jèhófà Ọlọ́run wa, Jèhófà kan ṣoṣo ni, kí o sì fi gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo ara rẹ àti gbogbo èrò rẹ àti gbogbo okun rẹ nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run rẹ.’ Ìkejì ni, ‘Kí o nífẹ̀ẹ́ ọmọnìkejì rẹ bí ara rẹ.’ Kò sí àṣẹ míì tó tóbi ju àwọn yìí lọ.”—Máàkù 12:29-31.

Lẹ́yìn tí Jésù dáhùn, ọkùnrin náà sọ pé: “Olùkọ́, ohun tí o sọ dáa, ó sì bá òtítọ́ mu, ‘Ọ̀kan ṣoṣo ni Òun, kò sí ẹlòmíì àfi òun nìkan’; kí èèyàn fi gbogbo ọkàn, gbogbo òye àti gbogbo okun nífẹ̀ẹ́ Rẹ̀, kó sì nífẹ̀ẹ́ ọmọnìkejì rẹ̀ bí ara rẹ̀ ṣe pàtàkì gan-an ju gbogbo odindi ẹbọ sísun àtàwọn ẹbọ.” Nígbà tí Jésù rí i pé ìdáhùn rẹ̀ mọ́gbọ́n dání, ó sọ fún un pé: “O ò jìnnà sí Ìjọba Ọlọ́run.”—Máàkù 12:32-34.

Ó ti tó ọjọ́ mẹ́ta báyìí tí Jésù ti ń kọ́ àwọn èèyàn nínú tẹ́ńpìlì (ìyẹn Nísàn 9, Nísàn 10 àti Nísàn 11). Ọ̀pọ̀ èèyàn ló sì ń fara balẹ̀ tẹ́tí sí i, títí kan àwọn akọ̀wé òfin. Àmọ́ àwọn aṣáájú ẹ̀sìn ò nífẹ̀ẹ́ sí ohun tó ń sọ, wọn ò sì “láyà láti tún bi í ní ìbéèrè mọ́.”