Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 126

Pétérù Sẹ́ Jésù Nílé Káyáfà

Pétérù Sẹ́ Jésù Nílé Káyáfà

Nígbà tí wọ́n mú Jésù nínú ọgbà Gẹ́tísémánì, ẹ̀rù ba àwọn àpọ́sítélì rẹ̀, wọ́n sì sá lọ. Àmọ́ méjì nínú wọn pa dà. Àwọn tó pa dà ni Pétérù “àti ọmọ ẹ̀yìn míì” tó ṣeé ṣe kó jẹ́ àpọ́sítélì Jòhánù. (Jòhánù 18:15; 19:35; 21:24) Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé bí wọ́n ṣe ń mú Jésù lọ sílé Ánásì ni wọ́n ń yọ́ tẹ̀ lé e. Nígbà tí Ánásì ní kí wọ́n mú Jésù lọ sọ́dọ̀ Káyáfà tó jẹ́ àlùfáà àgbà, Pétérù àti Jòhánù rọra ń tẹ̀ lé wọn bọ̀ lẹ́yìn. Ó ṣeé ṣe kí ẹ̀rù ikú máa ba àwọn àpọ́sítélì yìí, wọ́n sì lè máa ṣàníyàn nípa ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí Ọ̀gá wọn.

Àlùfáà àgbà mọ Jòhánù, torí náà ó rọrùn fún un láti wọnú àgbàlá ilé Káyáfà. Àmọ́ ẹnu ọ̀nà ni Pétérù dúró sí ní tiẹ̀. Nígbà tó yá, Jòhánù pa dà wá bá ìránṣẹ́bìnrin tó ń ṣọ́ ẹnu ọ̀nà náà sọ̀rọ̀, ó sì jẹ́ kí Pétérù wọlé.

Òtútù mú lálẹ́ ọjọ́ yẹn, torí náà, àwọn tó wà nínú àgbàlá yẹn ń yáná. Pétérù jókòó tì wọ́n kóun náà lè yáná, kó sì lè “mọ ibi tọ́rọ̀ yẹn máa já sí” fún Jésù. (Mátíù 26:58) Ìmọ́lẹ̀ iná tí wọ́n dá nínú àgbàlá yẹn wá jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin tó ṣílẹ̀kùn fún Pétérù ríran rí i dáadáa. Ló bá bi í pé: “Ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ọkùnrin yìí ni ọ́, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́?” (Jòhánù 18:17) Obìnrin yìí nìkan kọ́ ló dá Pétérù mọ̀, àwọn míì náà wà níbẹ̀, gbogbo wọn ló sì ń fẹ̀sùn kan Pétérù pé ọmọ ẹ̀yìn Jésù ni.—Mátíù 26:69, 71-73; Máàkù 14:70.

Inú bí Pétérù gan-an. Kò fẹ́ kí wọ́n dá òun mọ̀, kódà, ṣe ló rọra ń sún mọ́ ẹnu ọ̀nà. Torí náà, ó sẹ́ pé òun ò mọ Jésù, ó ní: “Mi ò mọ̀ ọ́n, ohun tí ò ń sọ ò sì yé mi.” (Máàkù 14:67, 68) Kódà, ó tún “gégùn-ún, ó sì ń búra,” ohun tó ń sọ ni pé òun ṣe tán láti búra kí wọ́n lè mọ̀ pé òótọ́ lọ̀rọ̀ òun, òun ò sì kọ̀ kí ìyà jẹ òun tó bá jẹ́ pé irọ́ lòun pa.—Mátíù 26:74.

Lákòókò yẹn, wọ́n ń gbọ́ ẹjọ́ Jésù lọ́wọ́, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ apá ibì kan lókè nínú ilé Káyáfà ni wọ́n wà. Ó ṣeé ṣe kí Pétérù àtàwọn tó wà nísàlẹ̀ máa rí báwọn èèyàn ṣe ń wọlé, tí wọ́n ń jáde láti wá jẹ́rìí lòdì sí Jésù.

Torí pé ará Gálílì ni Pétérù, bó ṣe ń sọ̀rọ̀ ti jẹ́ kó hàn pé irọ́ ló ń pa. Yàtọ̀ síyẹn, ẹnì kan wà níbẹ̀ tó jẹ́ mọ̀lẹ́bí Málíkọ́sì tí Pétérù gé etí rẹ̀ dà nù. Ẹni yẹn wá fẹ̀sùn kan Pétérù pé: “Mo rí ọ pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọgbà, àbí mi ò rí ọ?” Pétérù tún sẹ́ lẹ́ẹ̀kẹta, ni àkùkọ bá kọ, bí Jésù ṣe sọ tẹ́lẹ̀.—Jòhánù 13:38; 18:26, 27.

Lásìkò yẹn, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé bákónì tó wà lókè ni Jésù wà, tó sì ń wo àgbàlá tó wà nísàlẹ̀. Jésù wá yíjú sí Pétérù, ojú àwọn méjèèjì sì ṣe mẹ́rin, ó ká Pétérù lára gan-an. Ẹ wo bó ṣe máa dùn ún tó, nígbà tó rántí ohun tí Jésù sọ ní wákàtí mélòó kan sẹ́yìn àtohun tó tún wá ṣe sí Jésù báyìí. Ó bọ́ síta, ó sì ń sunkún gidigidi.—Lúùkù 22:61, 62.

Ìyẹn ni pé Pétérù lè sẹ́ Jésù pẹ̀lú bó ṣe fi gbogbo ẹnu sọ pé mìmì kan ò lè mi òun? Pétérù rí i pé ṣe ni wọ́n parọ́ mọ́ Jésù, tí wọ́n sì fẹ̀sùn èké kàn án pé ọ̀daràn paraku ni. Àǹfààní nìyí fún Pétérù láti gbèjà Ọ̀gá rẹ̀ tó jẹ́ aláìṣẹ̀, àmọ́ ṣe ló kẹ̀yìn sí Ẹni tó ní “ọ̀rọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun,” tó sì sọ pé òun ò mọ̀ ọ́n rí.—Jòhánù 6:68.

Ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Pétérù jẹ́ ká rí i pé tá ò bá múra sílẹ̀ dáadáa, tí àjálù tàbí àdánwò bá dé láìròtẹ́lẹ̀, kódà ẹni tó nígbàgbọ́ tó sì sún mọ́ Ọlọ́run lè juwọ́ sílẹ̀. Torí náà, ó máa dáa kí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Pétérù jẹ́ ìkìlọ̀ fún gbogbo àwa ìránṣẹ́ Ọlọ́run!