Tó O Bá Fẹ́ Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Jésù, Ó Yẹ Kó O . . .
MÁA ṢÀÁNÚ
Àwọn èèyàn máa ń ní ẹ̀dùn ọkàn, wọ́n sì máa ń ṣàníyàn. Àmọ́ ọ̀rọ̀ Jésù ò rí bẹ́ẹ̀ torí pé ẹni pípé ni. Síbẹ̀, ó máa ń fi hàn pé òun nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn dénú. Ó múra tán láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, kódà ó máa ń ṣe kọjá ohun táwọn èèyàn retí. Àánú tó ní sáwọn èèyàn ló ń sún un láti ràn wọ́n lọ́wọ́. Wàá rí àpẹẹrẹ bí Jésù ṣe ṣe èyí ní Orí 32, 37, 57, 99.
JẸ́ ẸNI TÓ ṢEÉ SÚN MỌ́
MÁA GBÀDÚRÀ NÍGBÀ GBOGBO
Jésù máa ń gbàdúrà àtọkànwá sí Baba rẹ̀ déédéé, ó sì máa ń ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tó bá dá wà àti nígbà tó bá wà láàárín àwọn olùjọsìn tòótọ́. Gbogbo ìgbà ni Jésù máa ń gbàdúrà, kì í ṣe ìgbà tó bá fẹ́ jẹun nìkan. Nínú àdúrà rẹ̀, ó máa ń dúpẹ́, á yin Baba rẹ̀, ó sì máa ń béèrè fún ìtọ́sọ́nà Baba rẹ̀ tó bá fẹ́ ṣe àwọn ìpinnu tó lágbára. Wàá rí àpẹẹrẹ èyí ní Orí 24, 34, 91, 122, 123.
MÁA WÁ IRE ÀWỌN MÍÌ
MÁA DÁRÍ JINI
JẸ́ ONÍTARA
Àsọtẹ́lẹ̀ ti wà pé àwọn Júù ò ní gbà pé Jésù ni Mèsáyà àti pé àwọn ọ̀tá ló máa pa á. Torí náà Jésù lè yàn pé òun ò ní lo gbogbo okun òun fáwọn èèyàn. Àmọ́ kò ṣe bẹ́ẹ̀, ṣe ló fìtara ti ìjọsìn tòótọ́ lẹ́yìn. Ó fi àpẹẹrẹ àtàtà lélẹ̀ fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀, kí wọ́n máa fìtara wàásù báwọn èèyàn tiẹ̀ ń ta kò wọ́n, tí wọ́n sì ń ṣenúnibíni sí wọn. Wo Orí 16, 72, 103.