Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú

Ọ̀rọ̀ Ìṣáájú

ỌLỌ́RUN OLÓDÙMARÈ ni Ọba Aláṣẹ ayé òun ọ̀run. Ọwọ́ rẹ̀ ni ìwàláàyè wa ìsinsìnyí àti ti ọjọ́ iwájú wà. Ó lágbára láti sanni lẹ́san rere, ó sì lágbára láti fìyà jẹni. Ó lágbára láti fúnni ní ìyè, ó sì lágbára láti gbà á. Bí a bá rí ojú rere rẹ̀, a ó ṣe àṣeyọrí sí rere; bí èèyàn ò bá rí ojú rere rẹ̀, a jẹ́ pé ó parí fónítọ̀hún nìyẹn. Ẹ ò rí i pé ó ṣe pàtàkì gan-an kí ìjọsìn wa ní ìtẹ́wọ́gbà rẹ̀!

Oríṣiríṣi ọ̀nà làwọn èèyàn ń gbà jọ́sìn. Bí ìsìn bá dà bí ọ̀nà, ǹjẹ́ gbogbo ọ̀nà ìjọsìn ni Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà? Rárá o, kì í ṣe gbogbo wọn. Jésù, tó jẹ́ wòlíì Ọlọ́run fi hàn pé ọ̀nà méjì péré ní gbogbo wọ́n pín sí. Ó sọ pé: “Aláyè gbígbòòrò ni ojú ọ̀nà tí ó lọ sínú ìparun, ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì ni àwọn tí ń gbà á wọlé; nígbà tí ó jẹ́ pé, tóóró ni ẹnubodè náà, híhá sì ni ojú ọ̀nà tí ó lọ sínú ìyè, díẹ̀ sì ni àwọn tí ń rí i.”​—Mátíù 7:13, 14.

Oríṣi ìsìn méjì péré ló wà: ọ̀kan ń sinni lọ sí ìyè, èkejì sì ń sinni lọ sí ìparun. Ohun tí ìwé pẹlẹbẹ yìí wà fún ni pé kí ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti rí ọ̀nà tó lọ sí ìyè àìnípẹ̀kun.