Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 9

“Kristi Ni Agbára Ọlọ́run”

“Kristi Ni Agbára Ọlọ́run”

1-3. (a) Kí ló ṣẹlẹ̀ sáwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù lórí Òkun Gálílì, kí ni Jésù sì ṣe? (b) Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi sọ pé “Kristi ni agbára Ọlọ́run”?

 LỌ́JỌ́ kan, báwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ṣe ń wa ọkọ̀ ojú omi lọ lórí Òkun Gálílì, ìjì líle bẹ̀rẹ̀. Ẹ̀rù bà wọ́n gan-an! Òótọ́ ni pé ìyẹn kọ́ nìgbà àkọ́kọ́ tí wọ́n máa rí i tí ìjì ń jà lórí òkun, ó ṣe tán ó pẹ́ tí ọ̀pọ̀ lára wọn ti ń ṣe iṣẹ́ apẹja. a (Mátíù 4:18, 19) Àmọ́, tọ̀tẹ̀ yìí yàtọ̀, torí pé ‘ìjì náà le gan-an, ó sì ń fẹ́ atẹ́gùn gidigidi,’ ó le débi pé kíá ni gbogbo ojú òkun dà rú, tó sì ń ru gùdù. Torí náà, láìka báwọn ọkùnrin yẹn ṣe ń gbìyànjú tó, kò rọrùn fún wọn láti darí ọkọ̀ wọn. Ńṣe ni ‘ìgbì òkun ń rọ́ wọnú ọkọ̀ ojú omi náà ṣáá,’ tí omi sì ń kún inú rẹ̀. Ní gbogbo àsìkò táwọn ọmọ ẹ̀yìn fi ń ṣe wàhálà yẹn, ńṣe ni Jésù ń sùn torí pé àtàárọ̀ ló ti ń kọ́ àwọn èèyàn, ó sì ti rẹ̀ ẹ́ gan-an. Nígbà tó yá, ẹ̀rù bẹ̀rẹ̀ sí í bà wọ́n pé wọ́n lè kú sínú omi náà, ni wọ́n bá lọ jí Jésù, wọ́n sì sọ fún un pé: “Olúwa, gbà wá, a ti fẹ́ ṣègbé!”​—Máàkù 4:35-38; Mátíù 8:23-25.

2 Ẹ̀rù ò ba Jésù ní tiẹ̀, ó mọ̀ pé òun lágbára láti bá ìgbì òkun náà wí. Torí náà, ó sọ fún ìjì náà pé: “Ó tó! Dákẹ́ jẹ́ẹ́!” Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni ìgbì òkun náà rọlẹ̀, ìjì náà sì dáwọ́ dúró, “ni gbogbo ẹ̀ bá pa rọ́rọ́.” Ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn dẹ́rù ba àwọn ọmọ ẹ̀yìn náà gan-an, ni wọ́n bá ń bi ara wọn pé: “Ta lẹni yìí gan-an?” Ó yà wọ́n lẹ́nu gan-an bí wọ́n ṣe rí i tí èèyàn ń bá ìgbì òkun wí bí ìgbà tó ń bá ọmọ tó ń ṣe ìjàngbọ̀n wí.​—Máàkù 4:39-41; Mátíù 8:26, 27.

3 Kí ló mú kí Jésù lè ṣe ohun tó ṣe yẹn? Jèhófà ló fún un lágbára, òun ló sì jẹ́ kó lè ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ lọ́nà tó ṣàrà ọ̀tọ̀. Ìdí nìyẹn tí Ọlọ́run fi mí sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù láti sọ pé “Kristi ni agbára Ọlọ́run.” (1 Kọ́ríńtì 1:24) Àwọn nǹkan wo ni Jésù ṣe tó jẹ́ ká mọ bí Ọlọ́run ṣe lágbára tó? Báwo la ṣe lè jàǹfààní látinú agbára tí Jèhófà fún Jésù?

Agbára Ọmọ Bíbí Kan Ṣoṣo Ọlọ́run

4, 5. (a) Kí ni Jèhófà fún Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo lágbára láti ṣe? (b) Kí ni Jèhófà fún Jésù kó lè ràn án lọ́wọ́ láti dá àwọn nǹkan?

4 Ronú nípa agbára tí Jésù ní kó tó wá sáyé. Jèhófà lo “agbára ayérayé” rẹ̀ láti dá Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo, Ọmọ yìí la wá mọ̀ sí Jésù Kristi nígbà tó yá. (Róòmù 1:20; Kólósè 1:15) Lẹ́yìn náà, Jèhófà fún Ọmọ rẹ̀ yìí ní agbára tó pọ̀ gan-an, ó sì ní kó ran òun lọ́wọ́ láti dá àwọn nǹkan. Bíbélì sọ nípa Ọmọ yìí pé: “Ohun gbogbo wà nípasẹ̀ rẹ̀ àti pé láìsí i, kò sí nǹkan kan tó wà.”​—Jòhánù 1:3.

5 Fojú inú wo bí agbára tí Ọlọ́run fún Jésù nígbà yẹn ṣe máa pọ̀ tó. Ó dájú pé agbára kékeré kọ́ ló fi dá àìmọye àwọn áńgẹ́lì alágbára, àìmọye bílíọ̀nù ìṣùpọ̀ ìràwọ̀ àti àìmọye ìràwọ̀ tó wà nínú ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, títí kan ayé àti onírúurú ohun alààyè tó wà nínú rẹ̀. Ọlọ́run fún Ọmọ bíbí kan ṣoṣo yìí ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ kó lè ṣe iṣẹ́ náà yanjú, torí pé ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ló lágbára jù lọ láyé àti lọ́run. Inú Jésù dùn gan-an pé òun ni Àgbà Òṣìṣẹ́ tí Jèhófà lò láti dá gbogbo nǹkan tó kù láyé àti lọ́run.​—Òwe 8:22-31.

6. Agbára àti àṣẹ wo ni Ọlọ́run fún Jésù lẹ́yìn tó kú tó sì jíǹde?

6 Ṣé nǹkan míì tún wà tí Jèhófà lè fún Ọmọ bíbí kan ṣoṣo yìí lágbára láti ṣe? Lẹ́yìn tí Jésù kú tó sì jíǹde, ó sọ pé: “Gbogbo àṣẹ ní ọ̀run àti ayé la ti fún mi.” (Mátíù 28:18) Èyí fi hàn pé Ọlọ́run ti fún Jésù ní àṣẹ láti jọba lórí ohun gbogbo láyé àti lọ́run. Jèhófà ti fi Jésù ṣe “Ọba àwọn ọba àti Olúwa àwọn olúwa,” ó sì ti fún un ní àṣẹ láti “sọ gbogbo ìjọba àti gbogbo àṣẹ àti agbára” tó bá ta ko òun “di asán,” yálà èyí tó ṣeé fojú rí tàbí èyí tí kò ṣeé fojú rí. (Ìfihàn 19:16; 1 Kọ́ríńtì 15:24-26) Jèhófà ti fún Jésù ní àṣẹ láti darí ohun gbogbo, ẹnì kan ṣoṣo tí ò sí lábẹ́ Jésù ni Jèhófà fúnra rẹ̀.​—Hébérù 2:8; 1 Kọ́ríńtì 15:27.

7. Kí ló mú kó dá wa lójú pé Jésù ò ní ṣi agbára tí Jèhófà fún un lò láé?

7 Ṣé ó yẹ kẹ́rù máa bà wá pé Jésù lè ṣi agbára rẹ̀ lò? Rárá o! Jésù fẹ́ràn Bàbá rẹ̀ gan-an, torí náà kò lè ṣe ohunkóhun tó máa bí i nínú. (Jòhánù 8:29; 14:31) Jésù mọ̀ pé agbára Jèhófà ò láàlà, ó sì mọ̀ pé Jèhófà ò ṣi agbára yẹn lò rí. Ọ̀pọ̀ ìgbà ni Jésù ti rí i tí Jèhófà ń “fi agbára rẹ̀ hàn nítorí àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sìn ín.” (2 Kíróníkà 16:9) Jésù fẹ́ràn àwọn èèyàn bí Bàbá ẹ̀ ṣe fẹ́ràn wọn, torí náà ó dá wa lójú pé gbogbo ìgbà láá máa fi agbára rẹ̀ ṣe àwa èèyàn láǹfààní. (Jòhánù 13:1) Àwọn nǹkan tó ti ṣe sẹ́yìn jẹ́rìí sí i pé òótọ́ ni. Ẹ jẹ́ ká sọ̀rọ̀ nípa bí Jésù ṣe lo agbára rẹ̀ nígbà tó wà láyé, ká sì wo ohun tó mú kó lo agbára náà.

‘Alágbára Nínú Ọ̀rọ̀’

8. Lẹ́yìn tí Ọlọ́run fi ẹ̀mí mímọ́ yan Jésù, kí ló fún un lágbára láti ṣe, báwo ló sì ṣe lo agbára náà?

8 Ẹ̀rí fi hàn pé Jésù ò ṣe iṣẹ́ ìyanu kankan nígbà tó wà ní kékeré ní Násárẹ́tì. Àmọ́, nǹkan yí pa dà lẹ́yìn tó ṣèrìbọmi lọ́dún 29 Sànmánì Kristẹni, nígbà tó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ẹni ọgbọ̀n (30) ọdún. (Lúùkù 3:21-23) Bíbélì sọ nípa Jésù pé: ‘Ọlọ́run fi ẹ̀mí mímọ́ àti agbára yàn án, ó sì lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ó ń ṣe rere, ó sì ń wo gbogbo àwọn tí Èṣù ń ni lára sàn.’ (Ìṣe 10:38) Bí Ìwé Mímọ́ ṣe sọ pé Jésù “ń ṣe rere” jẹ́ ká rí i pé ó ń lo agbára rẹ̀ láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́. Lẹ́yìn tí Ọlọ́run fi ẹ̀mí mímọ́ yan Jésù, ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àwọn nǹkan tó “fi hàn pé wòlíì tó lágbára ni òun nínú ọ̀rọ̀ àti ìṣe.”​—Lúùkù 24:19.

9-11. (a) Ibo ni Jésù ti sábà máa ń kọ́ni, ìṣòro wo ló sì ṣeé ṣe kó ní? (b) Kí nìdí tí ọ̀nà tí Jésù gbà ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ fi ya àwọn èrò náà lẹ́nu?

9 Báwo ni Jésù ṣe jẹ́ alágbára nínú ọ̀rọ̀? Ó sábà máa ń kọ́ni ní ìta gbangba, irú bí etíkun, ẹ̀gbẹ́ òkè, ojú ọ̀nà àti ọjà. (Máàkù 6:53-56; Lúùkù 5:1-3; 13:26) Ká sọ pé ọ̀rọ̀ Jésù kì í wọ àwọn èèyàn lọ́kàn, ńṣe ni wọ́n kàn máa kúrò níbi tó ti ń bá wọn sọ̀rọ̀. Bó tún ṣe jẹ́ pé ojú ẹsẹ̀ kọ́ ni wọ́n kọ àwọn ọ̀rọ̀ ẹ̀ sílẹ̀ nígbà yẹn, àwọn tó ń gbọ́rọ̀ ẹ̀ gbọ́dọ̀ fọkàn sí ohun tó ń sọ. Torí náà, Jésù ní láti kọ́ àwọn èèyàn dáadáa kí ọ̀rọ̀ ẹ̀ lè wọ̀ wọ́n lọ́kàn, kó sì yé wọn, kí wọ́n má bàa gbàgbé. Tá a bá sì wo bí Jésù ṣe kọ́ni nínú Ìwàásù Orí Òkè, àá rí i pé ìyẹn ò ṣòro fún un rárá.

10 Láàárọ̀ ọjọ́ kan lápá ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 31 Sànmánì Kristẹni, àwùjọ èèyàn kan kóra jọ sẹ́gbẹ̀ẹ́ òkè kan tó wà nítòsí Òkun Gálílì. Àwọn kan lára wọn wá láti Jùdíà àti Jerúsálẹ́mù, ìyẹn sì jìn tó nǹkan bí ọgọ́rùn-ún (100) tàbí àádọ́fà (110) kìlómítà. Àwọn míì wá láti etíkun Tírè àti Sídónì lápá àríwá. Ọ̀pọ̀ àwọn aláìsàn ló sún mọ́ Jésù kí wọ́n lè fọwọ́ kàn án, ó sì wo gbogbo wọn sàn. Lẹ́yìn náà, Jésù bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn. (Lúùkù 6:17-19) Nígbà tó parí ọ̀rọ̀ rẹ̀, àwọn nǹkan tó sọ ya àwọn èèyàn náà lẹ́nu. Kí nìdí?

11 Ní ọdún mélòó kan lẹ́yìn yẹn, ọkàn lára àwọn tó gbọ́ ìwàásù yẹn kọ̀wé pé: “Bó ṣe ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ ya àwọn èrò náà lẹ́nu, torí ṣe ló ń kọ́ wọn bí ẹni tó ní àṣẹ.” (Mátíù 7:28, 29) Ohun tí Jésù kọ́ àwọn èèyàn náà jẹ́ kí wọ́n rí i pé alágbára ni lóòótọ́. Bí àpẹẹrẹ, ó ń kọ́ àwọn èèyàn ní òtítọ́ nípa Ọlọ́run, gbogbo ohun tó ń kọ́ni ló sì bá Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mu. (Jòhánù 7:16) Àwọn ẹ̀kọ́ Jésù ò lọ́jú pọ̀ rárá, ọ̀rọ̀ ẹ̀ sì máa ń mú káwọn èèyàn ronú jinlẹ̀. Ó máa ń rọrùn fáwọn èèyàn láti tẹ̀ lé ìmọ̀ràn ẹ̀, gbogbo ọ̀rọ̀ ẹ̀ ló sì ṣeé gbára lé. Kì í fòótọ́ pa mọ́, ó sì máa ń sọ àwọn nǹkan tó máa jẹ́ káwọn èèyàn yẹ ara wọn wò, kí wọ́n lè ṣàtúnṣe tó yẹ. Ó jẹ́ káwọn èèyàn mọ bí wọ́n ṣe lè láyọ̀, bí wọ́n ṣe lè máa gbàdúrà, bí wọ́n ṣe lè máa wá Ìjọba Ọlọ́run, àti ohun tí wọ́n lè ṣe kí ọjọ́ ọ̀la wọn lè dáa. (Mátíù 5:3–7:27) Ọ̀rọ̀ ẹ̀ ran àwọn tó nífẹ̀ẹ́ òtítọ́ lọ́wọ́ kí wọ́n lè máa ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́. Kódà wọ́n múra tán láti “sẹ́” ara wọn, kí wọ́n sì pa ohun gbogbo tì, kí wọ́n lè máa tẹ̀ lé e. (Mátíù 16:24; Lúùkù 5:10, 11) Èyí jẹ́ ká rí i pé ọ̀rọ̀ Jésù lágbára gan-an!

‘Alágbára Nínú Ìṣe’

12, 13. Ọ̀nà wo ni Jésù gbà jẹ́ ‘alágbára nínú ìṣe,’ oríṣiríṣi iṣẹ́ ìyanu wo ló sì ṣe?

12 Jésù tún jẹ́ ‘alágbára nínú ìṣe.’ (Lúùkù 24:19) Ó ju ọgbọ̀n (30) iṣẹ́ ìyanu táwọn Ìwé Ìhìn Rere sọ pé Jésù ṣe, “agbára Jèhófà” ló sì fi ṣe gbogbo wọn. b (Lúùkù 5:17) Ọ̀pọ̀ èèyàn ló jàǹfààní iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe. Bí àpẹẹrẹ, ìgbà kan wà tó pèsè oúnjẹ fún ẹgbẹ̀rún márùn-ún (5,000) ọkùnrin lọ́nà ìyanu, ó tún pèsè oúnjẹ fún ẹgbẹ̀rún mẹ́rin (4,000) ọkùnrin lásìkò míì. Ká sọ pé wọ́n ka àwọn obìnrin àtàwọn ọmọdé tó wà níbẹ̀ ni, ó dájú pé iye àwọn tó pèsè oúnjẹ fún máa pọ̀ jù bẹ́ẹ̀ lọ gan-an!​—Mátíù 14:13-21; 15:32-38.

13 Oríṣiríṣi iṣẹ́ ìyanu ni Jésù ṣe. Bí àpẹẹrẹ, ó láṣẹ lórí àwọn ẹ̀mí èṣù, ó sì máa ń rọrùn fún un láti lé wọn jáde. (Lúùkù 9:37-43) Ó lágbára lórí àwọn nǹkan tí Ọlọ́run dá, irú bí ìjì àti omi. Kódà, ó sọ omi di wáìnì. (Jòhánù 2:1-11) Wo bó ṣe máa rí lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn nígbà tí “wọ́n rí Jésù tó ń rìn lórí òkun.” (Jòhánù 6:18, 19) Yàtọ̀ síyẹn, Jésù lágbára lórí oríṣiríṣi àìsàn, kódà ó mú àwọn tó ń ṣàìsàn tó le gan-an lára dá, títí kan àwọn tó ní àrùn tí kò gbóògùn. (Máàkù 3:1-5; Jòhánù 4:46-54) Oríṣiríṣi ọ̀nà ló gbà mú àwọn tó ń ṣàìsàn lára dá. Jésù ò sí nítòsí àwọn kan nígbà tó wò wọ́n sàn, àwọn míì sì wà tó jẹ́ pé ṣe ló fọwọ́ kàn wọ́n nígbà tó ń wò wọ́n sàn. (Mátíù 8:2, 3, 5-13) Àwọn kan wà tí Jésù wò sàn lójú ẹsẹ̀, àwọn míì sì wà tó wò sàn díẹ̀díẹ̀.​—Máàkù 8:22-25; Lúùkù 8:43, 44.

“Wọ́n rí Jésù tó ń rìn lórí òkun”

14. Àwọn ipò tó yàtọ̀ síra wo ni Jésù ti fi hàn pé òun lágbára láti jí òkú dìde?

14 Ohun kan tó ṣàrà ọ̀tọ̀ jù lọ lára àwọn nǹkan tí Jésù lágbára láti ṣe ni pé ó lè jí òkú dìde. Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tó ṣe bẹ́ẹ̀, ìyẹn ìgbà tó jí ọmọbìnrin kan tó jẹ́ ọmọ ọdún méjìlá dìde fáwọn òbí ẹ̀, ìgbà tó jí ọmọ kan ṣoṣo tí obìnrin opó kan bí dìde àtìgbà tó jí ọkùnrin kan dìde fáwọn arábìnrin ẹ̀. (Lúùkù 7:11-15; 8:49-56; Jòhánù 11:38-44) Kò sí ìkankan nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tó nira fún Jésù láti jí dìde. Bí àpẹẹrẹ, kò pẹ́ tí ọmọbìnrin yẹn kú tí Jésù fi jí i dìde, kódà wọn ò tíì gbé e kúrò lórí ibi tó kú sí. Orí àga ìgbókùú ni ọmọkùnrin opó yẹn ṣì wà nígbà tí Jésù jí i dìde, ó sì dájú pé ọjọ́ yẹn gangan ló kú. Bákan náà, ẹ̀yìn ọjọ́ kẹrin tí Lásárù kú ni Jésù jí i dìde kúrò nínú ibojì.

Jésù Máa Ń Fi Agbára Ẹ̀ Ran Àwọn Èèyàn Lọ́wọ́

15, 16. Ẹ̀rí wo ló fi hàn pé Jésù ò mọ tara ẹ̀ nìkan bó ṣe ń lo agbára tí Jèhófà fún un?

15 Ká sọ pé èèyàn aláìpé ni Ọlọ́run fún nírú agbára tí Jésù ní yìí, ńṣe lẹ̀rù á máa bà wá pé ẹni náà máa ṣi agbára yẹn lò. Ìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀ ni pé àwọn èèyàn tó wà nípò àṣẹ sábà máa ń mọ tara wọn nìkan, wọ́n máa ń gbéra ga, wọ́n tún máa ń ṣojúkòkòrò, ìyẹn sì máa ń jẹ́ kí wọ́n lo agbára wọn láti fi ni àwọn èèyàn lára. Àmọ́ Jésù ò ṣe bẹ́ẹ̀ ní tiẹ̀, torí pé ẹni pípé ni.​—1 Pétérù 2:22

16 Jésù ò mọ tara ẹ̀ nìkan, kàkà bẹ́ẹ̀ ńṣe ló máa ń fi agbára ẹ̀ ran àwọn èèyàn lọ́wọ́. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí ebi ń pa á, ó kọ̀ láti sọ òkúta di búrẹ́dì. (Mátíù 4:1-4) Kò ní ohun ìní tó pọ̀, ìyẹn sì fi hàn pé kò lo agbára rẹ̀ láti fi kó ọrọ̀ jọ. (Mátíù 8:20) Bákan náà, tí Jésù bá ṣe iṣẹ́ ìyanu, agbára máa ń kúrò lára ẹ̀. Kódà, tó bá jẹ́ pé ẹnì kan péré ló mú lára dá, ó máa ń mọ̀ ọ́n lára pé agbára ti jáde lára òun. (Máàkù 5:25-34) Síbẹ̀ ó gbà káwọn èrò fọwọ́ kan òun, gbogbo wọn sì rí ìwòsàn. (Lúùkù 6:19) Ká sòótọ́, Jésù ò mọ tara ẹ̀ nìkan, ó nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn dénú, ó sì múra tán láti fi agbára rẹ̀ ràn wọ́n lọ́wọ́.

17. Báwo ni Jésù ṣe fi hàn pé òun máa ń fi ọgbọ́n lo agbára?

17 Jésù máa ń fi ọgbọ́n lo agbára ẹ̀. Kì í lo agbára rẹ̀ torí kó lè gbéra ga tàbí torí káwọn èèyàn lè máa kan sáárá sí i. (Mátíù 4:5-7) Bí àpẹẹrẹ, ó kọ̀ láti ṣe iṣẹ́ ìyanu nígbà tí Hẹ́rọ́dù ní kó ṣe é kóun lè mọ irú ẹni tó jẹ́. (Lúùkù 23:8, 9) Dípò tí Jésù á fi máa sọ bóun ṣe lágbára tó fáwọn èèyàn, ṣe ló sábà máa ń sọ fáwọn tó wò sàn pé kí wọ́n má sọ fún ẹnikẹ́ni. (Máàkù 5:43; 7:36) Kò fẹ́ káwọn èèyàn gbà pé òun ni Mèsáyà torí pé wọ́n gbọ́ nípa àwọn iṣẹ́ ìyanu tóun ṣe.​—Mátíù 12:15-19.

18-20. (a) Kí nìdí tí Jésù fi lo agbára rẹ̀ láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́? (b) Báwo ló ṣe rí lára ẹ nígbà tó o ronú nípa ọ̀nà tí Jésù gbà tọ́jú ọkùnrin kan tó nílò ìtọ́jú tó ṣàrà ọ̀tọ̀?

18 Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Jésù lágbára gan-an, ó yàtọ̀ pátápátá sáwọn alákòóso ayé yìí tó jẹ́ pé ṣe ni wọ́n máa ń lo agbára bó ṣe wù wọ́n láìka ti ìyà tó ń jẹ àwọn èèyàn sí. Ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn jẹ Jésù lógún ní tiẹ̀. Ó máa ń dùn ún gan-an tó bá rí i táwọn èèyàn ń jìyà, ó sì máa ń rí i pé òun wá nǹkan ṣe láti yanjú ìṣòro wọn. (Mátíù 14:14) Jésù nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn gan-an, ó tún máa ń fi ọ̀rọ̀ wọn ro ara ẹ̀ wò, ìyẹn sì máa ń mú kó lo agbára rẹ̀ láti ràn wọ́n lọ́wọ́. Àpẹẹrẹ kan tó wúni lórí wà nínú Máàkù 7:31-37.

19 Lọ́jọ́ kan, ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn gbé àwọn tó ń ṣàìsàn wá sọ́dọ̀ Jésù, ó sì wo gbogbo wọn sàn. (Mátíù 15:29, 30) Àmọ́, Jésù kíyè sí ọkùnrin kan láàárín wọn, tó nílò ìtọ́jú tó ṣàrà ọ̀tọ̀. Ọkùnrin náà ò gbọ́ràn, kò sì lè sọ̀rọ̀ dáadáa. Ó ṣeé ṣe kí Jésù ti kíyè sí i pé ẹ̀rù ń ba ọkùnrin náà tàbí pé ojú ń tì í. Torí náà, Jésù gba tiẹ̀ rò, ó sì mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn èrò yẹn. Jésù wá ṣe àwọn nǹkan táá jẹ́ kí ọkùnrin náà mọ ohun tóun fẹ́ ṣe fún un. Ó “ki ìka rẹ̀ bọ etí ọkùnrin náà méjèèjì, lẹ́yìn tó tutọ́, ó fọwọ́ kan ahọ́n rẹ̀.” c (Máàkù 7:33) Lẹ́yìn náà, Jésù wo ọ̀run, ó sì mí kanlẹ̀. Àwọn nǹkan tí Jésù ṣe yẹn máa jẹ́ kí ọkùnrin náà mọ̀ pé agbára Ọlọ́run ló fẹ́ fi wo òun sàn. Jésù wá sọ pé: “Là.” (Máàkù 7:34) Bó ṣe di pé ọkùnrin náà bẹ̀rẹ̀ sí í gbọ́rọ̀ nìyẹn, tó sì lè sọ̀rọ̀ ketekete.

20 Tá a bá ronú nípa bí Jésù ṣe gba tàwọn èèyàn rò, tó sì fìfẹ́ lo agbára tí Ọlọ́run fún un láti fi wò wọ́n sàn, ìyẹn máa tù wá nínú gan-an! Ọkàn wa balẹ̀ bá a ṣe mọ̀ pé Alákòóso tó jẹ́ aláàánú tó sì nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn ni Jèhófà yàn láti jẹ́ Ọba Ìjọba rẹ̀!

Àpẹẹrẹ Àwọn Nǹkan Tó Máa Ṣẹlẹ̀ Lọ́jọ́ Iwájú

21, 22. (a) Kí làwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe nígbà tó wà láyé jẹ́ ká mọ̀ nípa ohun tó máa ṣe lọ́jọ́ iwájú? (b) Torí pé Jésù lágbára lórí àwọn nǹkan tó wà láyé, kí la lè máa retí nígbà tó bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé?

21 Ṣe làwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe nígbà tó wà láyé kàn jẹ́ àpẹẹrẹ àwọn nǹkan àgbàyanu tó máa ṣe nígbà tó bá ń ṣàkóso ayé. Nínú ayé tuntun, Jésù tún máa ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu, á sì ṣe bẹ́ẹ̀ kárí ayé. Ẹ jẹ́ ká sọ̀rọ̀ nípa díẹ̀ lára àwọn nǹkan àgbàyanu tó máa ṣe nígbà yẹn.

22 Jésù máa tún gbogbo ohun táwọn èèyàn ti bà jẹ́ láyé yìí ṣe, kó lè rí bí Ọlọ́run ṣe fẹ́ kó rí níbẹ̀rẹ̀. Ìgbà kan wà tí Jésù mú kí ìjì líle rọlẹ̀, èyí jẹ́ ká rí i pé ó lágbára lórí àwọn nǹkan tó wà láyé. Torí náà, lábẹ́ Ìjọba Kristi, àwa èèyàn ò ní máa bẹ̀rù nítorí ìjì líle, ìmìtìtì ilẹ̀, òkè ayọnáyèéfín tó ń bú gbàù, tàbí àwọn àjálù míì. Kò sóhun tí Jésù ò mọ̀ nípa ayé yìí, torí òun ni Àgbà Òṣìṣẹ́ tí Jèhófà lò láti dá ayé àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀. Jésù mọ ọ̀nà tó dáa jù lọ láti bójú tó àwọn nǹkan tó wà láyé. Tí Jésù bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé, ó máa sọ ayé di Párádísè.​—Lúùkù 23:43.

23. Báwo ni Jésù ṣe máa pèsè ohun táwa èèyàn nílò nígbà tó bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé?

23 Ṣé Jésù máa lè pèsè gbogbo ohun táwa èèyàn nílò? Bẹ́ẹ̀ ni. Rántí pé Jésù fi ìwọ̀nba oúnjẹ bọ́ ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyàn, tí gbogbo wọn sì jẹ àjẹṣẹ́kù. Torí náà, ó dájú pé ebi ò ní pa wá mọ́ nígbà ìṣàkóso rẹ̀. Ká sòótọ́, tí oúnjẹ bá pọ̀ dáadáa, tí wọ́n sì ń pín in bó ṣe yẹ, a ò ní gbúròó ebi mọ́. (Sáàmù 72:16) Nígbà tí Jésù wà láyé, ó fi hàn pé òun lágbára lórí onírúurú àìsàn, ìyẹn jẹ́ ká rí i pé kò ní sí afọ́jú, adití, aláàbọ̀ ara àti arọ nínú Ìjọba rẹ̀. Ó dájú pé ó máa wo gbogbo wọn sàn, a ò sì ní gbúròó àìsàn mọ́ láé. (Àìsáyà 33:24; 35:5, 6) Bákan náà, Jésù jí òkú dìde, ìyẹn sì jẹ́ kó dá wa lójú pé tó bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé, ó máa jí àìmọye mílíọ̀nù èèyàn tó wà ní ìrántí Bàbá rẹ̀ dìde.​—Jòhánù 5:28, 29.

24. Bá a ṣe ń ronú nípa bí agbára Jésù ṣe pọ̀ tó, kí ló yẹ ká fi sọ́kàn, kí sì nìdí?

24 Tá a bá ń ronú nípa bí agbára Jésù ṣe pọ̀ tó, ó yẹ ká máa rántí pé àpẹẹrẹ Bàbá rẹ̀ ló ń tẹ̀ lé láìkù síbì kan. (Jòhánù 14:9) Torí náà, ọ̀nà tí Jésù gbà ń lo agbára jẹ́ ká mọ bí Jèhófà ṣe ń lo agbára. Bí àpẹẹrẹ, ronú nípa bí Jésù ṣe fìfẹ́ hàn sí ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan, tó sì wò ó sàn lọ́nà jẹ̀lẹ́ńkẹ́. Àánú adẹ́tẹ̀ yìí ṣe Jésù débi pé ó fọwọ́ kàn án, ó ní: “Mo fẹ́ bẹ́ẹ̀!” (Máàkù 1:40-42) Ńṣe ni Jèhófà ń lo irú àkọsílẹ̀ bí èyí láti sọ fún wa pé, ‘Bí mo ṣe ń lo agbára mi lẹ̀ ń rí yẹn o!’ Tó o bá ń ronú nípa bí Ọlọ́run wa Olódùmarè ṣe ń lo agbára ẹ̀ lọ́nà tó fi hàn pé ó nífẹ̀ẹ́ wa, ó dájú pé á máa wù ẹ́ láti yìn ín lógo, kó o sì máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀!

a Ọ̀pọ̀ ìgbà ni ìjì máa ń dédé jà lójú Òkun Gálílì. Ìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀ ni pé ibi tí òkun náà wà lọ sísàlẹ̀ gan-an (ó fi nǹkan bí ọgọ́rùn-ún méjì (200) mítà lọ sísàlẹ̀ ju ojú òkun), afẹ́fẹ́ ibẹ̀ sì sábà máa ń gbóná ju tàwọn òkun míì lọ. Torí náà, ìgbàkigbà ni ojú ọjọ́ lè yí pa dà níbẹ̀. Atẹ́gùn líle tó ń rọ́ wá láti orí Òkè Hámónì tó wà lápá àríwá máa ń fẹ́ lọ sí Àfonífojì Jọ́dánì. Torí náà, ojú ọjọ́ ti lè pa rọ́rọ́ tẹ́lẹ̀, àmọ́ kí ìjì líle bẹ̀rẹ̀ sí í jà lẹ́yìn ìṣẹ́jú bíi mélòó kan.

b Yàtọ̀ síyẹn, ìgbà míì wà táwọn Ìwé Ìhìn Rere sọ̀rọ̀ ṣókí nípa iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe níbì kan, tó sì jẹ́ pé ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu ló ṣe níbẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, ìgbà kan wà tí “gbogbo ìlú” wá sọ́dọ̀ rẹ̀, tó sì wo “ọ̀pọ̀” àwọn tó ń ṣàìsàn lára wọn sàn.​—Máàkù 1:32-34.

c Nígbà yẹn, ọ̀pọ̀ àwọn Júù àtàwọn tí kì í ṣe Júù ló gbà pé itọ́ wà lára ohun tí wọ́n lè fi woni sàn. Ó lè jẹ́ pé ńṣe ni Jésù tutọ́ kó lè jẹ́ kí ọkùnrin náà mọ̀ pé òun fẹ́ wò ó sàn. Èyí ó wù kó jẹ́, ó dájú pé itọ́ kọ́ ni Jésù fi wo ọkùnrin náà sàn.