Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 29

Kí Ẹ Lè “Mọ Ìfẹ́ Kristi”

Kí Ẹ Lè “Mọ Ìfẹ́ Kristi”

1-3. (a) Kí ló mú kó wu Jésù láti fìwà jọ Bàbá rẹ̀? (b) Kí la máa kọ́ nínú orí yìí?

 ṢÉ O ti rí ọmọ kékeré kan tó ń gbìyànjú láti ṣe bíi ti bàbá rẹ̀ rí? Ọmọ náà lè máa fara wé bàbá ẹ̀ nínú ìrìn, ọ̀rọ̀ àti ìṣe. Bọ́mọ náà bá ṣe ń dàgbà, ó lè bẹ̀rẹ̀ sí í ronú bíi ti bàbá ẹ̀, kó fìwà jọ ọ́, kí wọ́n sì jọ máa sin Ọlọ́run kan náà. Bẹ́ẹ̀ ni, tí bàbá kan bá nífẹ̀ẹ́ ọmọ ẹ̀, ọmọ náà á fẹ́ràn bàbá ẹ̀, á bọ̀wọ̀ fún un èyí á sì mú kó fẹ́ máa ṣe bíi ti bàbá ẹ̀.

2 Irú àjọṣe wo ló wà láàárín Jésù àti Baba rẹ̀? Ìgbà kan wà tí Jésù sọ pé: “Mo nífẹ̀ẹ́ Baba.” (Jòhánù 14:31) Ká sòótọ́, kò sẹ́ni tó lè nífẹ̀ẹ́ Jèhófà bíi ti Ọmọ yìí, torí pé ọjọ́ pẹ́ tó ti wà pẹ̀lú Bàbá rẹ̀ ṣáájú kí Bàbá rẹ̀ tó dá àwọn áńgẹ́lì tó kù. Torí pé Jésù nífẹ̀ẹ́ Bàbá rẹ̀ ló fi wù ú pé kó fìwà jọ ọ́.​—Jòhánù 14:9.

3 Láwọn orí tó ṣáájú nínú ìwé yìí, a sọ̀rọ̀ nípa bí Jésù ṣe fara wé agbára, ìdájọ́ òdodo àti ọgbọ́n Jèhófà lọ́nà tó pé. Àmọ́ báwo ni Jésù ṣe fìfẹ́ hàn bíi ti Bàbá rẹ̀? Ẹ jẹ́ ká kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà mẹ́ta tí Jésù gbà fìfẹ́ hàn, ìyẹn bó ṣe ni ẹ̀mí ìfara-ẹni-rúbọ, bó ṣe jẹ́ ẹlẹ́yinjú àánú àti bó ṣe múra tán láti dárí jini.

“Kò Sí Ẹni Tí Ìfẹ́ Rẹ̀ Ju Èyí Lọ”

4. Báwo ni Jésù ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ àtàtà tó bá di pé kéèyàn nífẹ̀ẹ́ látọkàn wá?

4 Tá a bá nífẹ̀ẹ́ ẹnì kan látọkàn wá, a máa múra tán láti yááfì ohunkóhun ká lè ran ẹni náà lọ́wọ́, tíyẹn bá tiẹ̀ gba pé ká kú torí ẹni náà. Àpẹẹrẹ àtàtà ni Jésù jẹ́ lórí ọ̀rọ̀ yìí. Báwo la ṣe mọ̀ bẹ́ẹ̀? Òun fúnra ẹ̀ sọ pé: “Kò sí ẹni tí ìfẹ́ rẹ̀ ju èyí lọ, pé kí ẹnì kan fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀.” (Jòhánù 15:13) Tọkàntọkàn ni Jésù fi gbà láti fi ẹ̀mí rẹ̀ pípé lélẹ̀ torí tiwa. Ohun tó ṣe yẹn ni ọ̀nà tó ga jù lọ tí ẹnikẹ́ni ti gbà fìfẹ́ hàn. Àmọ́ Jésù tún fi hàn pé òun nífẹ̀ẹ́ àwa èèyàn látọkàn wá láwọn ọ̀nà míì.

5. Àwọn nǹkan wo ni Ọmọ Ọlọ́run fi sílẹ̀ lọ́run kó lè wá sáyé?

5 Kí Ọmọ bíbí kan ṣoṣo Ọlọ́run tó wá sáyé, ipò ńlá ló wà lọ́run. Ó ní àjọṣe tímọ́tímọ́ pẹ̀lú Jèhófà àti ọ̀pọ̀ àwọn áńgẹ́lì. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé nǹkan ń lọ dáadáa fún Ọmọ ọ̀wọ́n yìí lọ́run, ó “fi gbogbo ohun tó ní sílẹ̀, ó gbé ìrísí ẹrú wọ̀, ó sì di èèyàn.” (Fílípì 2:7) Ó fínnúfíndọ̀ yọ̀ǹda ara ẹ̀ láti wá gbé láàárín àwọn èèyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú ayé tó “wà lábẹ́ agbára ẹni burúkú náà.” (1 Jòhánù 5:19) Ó dájú pé ohun tí Ọmọ Ọlọ́run ṣe yìí fi hàn pé ó nífẹ̀ẹ́ wa gan-an!

6, 7. (a) Àwọn nǹkan wo ni Jésù ṣe nígbà tó wà láyé tó fi hàn pé ó nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn gan-an? (b) Àpẹẹrẹ wo la rí nínú Jòhánù 19:25-27 nípa bí Jésù ṣe nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn látọkàn wá?

6 Jálẹ̀ gbogbo àsìkò tí Jésù fi ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ láyé, ọ̀pọ̀ nǹkan ló yááfì kó lè ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, ìyẹn sì fi hàn pé ó nífẹ̀ẹ́ wọn gan-an. Kò mọ tara ẹ̀ nìkan. Ọ̀pọ̀ nǹkan ló sì fi du ara ẹ̀ torí kó lè lo ọ̀pọ̀ àkókò lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀. Ó sọ pé: “Àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ní ihò, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ní ìtẹ́, àmọ́ Ọmọ èèyàn kò ní ibì kankan tó máa gbé orí rẹ̀ lé.” (Mátíù 8:20) Káfíńtà tó kọ́ṣẹ́ mọṣẹ́ ni Jésù, torí náà ó lè kọ́ ilé ńlá tó tura fún ara ẹ̀, tàbí kó máa ṣe àwọn àga tó jojú ní gbèsè, kó lè máa tà wọ́n, kó sì rówó gbádùn ara ẹ̀. Àmọ́, kò ṣe iṣẹ́ káfíńtà torí kó lè kó ọrọ̀ jọ.

7 Àpẹẹrẹ kan tó wọni lọ́kàn gan-an nípa bí Jésù ṣe nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn látọkàn wá wà nínú Jòhánù 19:25-27. Ronú nípa oríṣiríṣi nǹkan tó máa wà lọ́kàn Jésù lọ́sàn-án ọjọ́ tó máa kú. Bó ṣe ń joró lórí igi tí wọ́n kàn án mọ́, bẹ́ẹ̀ ló ń ronú nípa àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀, iṣẹ́ ìwàásù, àti ní pàtàkì jù lọ, bó ṣe máa jẹ́ adúróṣinṣin, táá sì dá orúkọ Bàbá rẹ̀ láre. Ká sòótọ́, ohun tí Jésù bá ṣe lọ́jọ́ yẹn ló máa pinnu bóyá àwa èèyàn máa láǹfààní láti wà láàyè títí láé tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́! Síbẹ̀, nígbà tó ku díẹ̀ kí Jésù kú, ó tún ṣe ohun tó fi hàn pé ó nífẹ̀ẹ́ Màríà ìyá rẹ̀ tó ṣeé ṣe kó ti di opó nígbà yẹn. Jésù ní kí àpọ́sítélì Jòhánù máa bá òun tọ́jú Màríà bó ṣe máa tọ́jú ìyá tiẹ̀, àpọ́sítélì náà wá mú Màríà lọ sílé ara ẹ̀. Èyí fi hàn pé Jésù ṣètò bí wọ́n á ṣe máa bójú tó ìyá rẹ̀ nípa tara àti bí wọ́n ṣe máa ràn án lọ́wọ́ kó lè túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà. Ẹ ò rí i pé àpẹẹrẹ àtàtà ni Jésù jẹ́ tó bá di pé ká fìfẹ́ hàn!

‘Àánú Wọn Ṣe É’

8. Kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí Bíbélì fi ṣàpèjúwe bọ́rọ̀ àwọn èèyàn ṣe ń ká Jésù lára tó?

8 Jésù máa ń ṣàánú àwọn èèyàn bíi ti Bàbá rẹ̀. Ìwé Mímọ́ jẹ́ ká mọ̀ pé tí Jésù bá rí ẹni tí ìyà ń jẹ, àánú ẹni náà máa ṣe é, ó sì máa wù ú kó ran ẹni náà lọ́wọ́. Nígbà tí Bíbélì ń sọ bí ọ̀rọ̀ àwọn èèyàn ṣe ká Jésù lára tó, ó sọ pé ‘àánú wọn ṣe é.’ Ọ̀mọ̀wé kan tó ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé: “Wọ́n máa ń fi ọ̀rọ̀ yìí ṣàpèjúwe . . . ìmọ̀lára tó jinlẹ̀ gan-an téèyàn máa ń ní látọkàn wá. Ọ̀rọ̀ yìí ló lágbára jù lọ nínú àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń lò nínú èdè Gíríìkì láti fi ṣàpèjúwe ẹni tó jẹ́ aláàánú.” Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ ìgbà tí Jésù ṣàánú àwọn èèyàn, tíyẹn sì mú kó ṣe ohun kan láti ràn wọ́n lọ́wọ́.

9, 10. (a) Kí nìdí tí Jésù àtàwọn àpọ́sítélì rẹ̀ fi fẹ́ lọ síbi tó dá? (b) Kí ni Jésù ṣe nígbà táwọn èèyàn ò jẹ́ kó ráyè sinmi, kí sì nìdí tó fi ṣe bẹ́ẹ̀?

9 Jésù máa ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run torí pé ó jẹ́ aláàánú. Ohun tó wà nínú Máàkù 6:30-34 jẹ́ ká mọ ìdí pàtàkì tí Jésù fi máa ń ṣàánú àwọn èèyàn. Fojú inú wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà táwọn àpọ́sítélì dé látibi tí wọ́n ti lọ wàásù. Iṣẹ́ náà ò rọrùn rárá, àmọ́ inú wọn ń dùn nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Jésù. Wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí wọ́n rí, tí wọ́n sì gbọ́ fún un. Bí ọ̀pọ̀ èrò ṣe rọ́ dé nìyẹn, tí wọn ò jẹ́ kí Jésù àtàwọn àpọ́sítélì rẹ̀ tiẹ̀ ráyè jẹun. Jésù kíyè sí i pé ó ti rẹ àwọn àpọ́sítélì òun. Ló bá sọ fún wọn pé: “Ẹ máa bọ̀, ẹ wá síbi tó dá ní ẹ̀yin nìkan, kí ẹ sì sinmi díẹ̀.” Ni wọ́n bá wọ ọkọ̀ ojú omi lọ síbì kan tó pa rọ́rọ́ ní ìpẹ̀kun àríwá Òkun Gálílì. Àmọ́, àwọn èrò náà rí wọn bí wọ́n ṣe ń lọ, àwọn míì sì gbọ́ nípa rẹ̀. Bí gbogbo wọn tún ṣe sáré gba etídò lọ sí apá àríwá náà nìyẹn, wọ́n sì débẹ̀ kí ọkọ̀ ojú omi náà tó gúnlẹ̀!

10 Ṣé inú bí Jésù torí pé àwọn èèyàn yẹn ò jẹ́ kí òun àtàwọn àpọ́sítélì ẹ̀ ráyè sinmi? Rárá o! Kàkà bẹ́ẹ̀, nígbà tó rí ọ̀pọ̀ èèyàn tó ń dúró dè é, àánú wọn ṣe é. Máàkù sọ pé: “Ó rí èrò rẹpẹtẹ, àánú wọn sì ṣe é, torí wọ́n dà bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́ àgùntàn. Ó wá bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn ní ọ̀pọ̀ nǹkan.” Jésù mọ̀ pé àwọn èèyàn yìí nílò ìtọ́sọ́nà Ọlọ́run. Torí ńṣe ni wọ́n dà bí àgùntàn tó ti sọ nù, tí kò sì ní olùṣọ́ àgùntàn tó máa darí wọn tàbí dáàbò bò wọ́n. Jésù mọ̀ pé àwọn aṣáájú ẹ̀sìn tó yẹ kí wọ́n máa tọ́jú àwọn àgùntàn Jèhófà ti pa wọ́n tì, wọn ò sì bójú tó wọn. (Jòhánù 7:47-49) Àánú àwọn èèyàn náà ṣe Jésù, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn “nípa ìjọba Ọlọ́run.” (Lúùkù 9:11) Kíyè sí i pé àánú àwọn èèyàn yẹn ṣe Jésù kó tiẹ̀ tó mọ̀ bóyá wọ́n máa gbọ́ ọ̀rọ̀ òun àbí wọn ò ní gbọ́. Lédè míì, kì í ṣe ẹ̀yìn ìgbà tí Jésù kọ́ àwọn èèyàn náà ló tó ṣàánú wọn, kàkà bẹ́ẹ̀ kó tó bẹ̀rẹ̀ sí í bá wọn sọ̀rọ̀ ni àánú wọn ti ṣe é, ìyẹn gan-an ló sì mú kó kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́.

“Ó na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fọwọ́ kàn án”

11, 12. (a) Báwo làwọn èèyàn ṣe máa ń ṣe sáwọn adẹ́tẹ̀ nígbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, àmọ́ kí ni Jésù ṣe nígbà tí ọkùnrin kan “tí ẹ̀tẹ̀ bò” lọ bá a? (b) Báwo ló ṣe rí lára adẹ́tẹ̀ yẹn nígbà tí Jésù fọwọ́ kàn án, kí lohun tí dókítà kan sọ sì jẹ́ ká mọ̀?

11 Jésù máa ń ran àwọn tó ń jìyà lọ́wọ́ torí pé ó jẹ́ aláàánú. Àwọn èèyàn tó ní onírúurú àìsàn rí i pé ẹlẹ́yinjú àánú ni Jésù, torí náà ó wù wọ́n kí wọ́n sún mọ́ ọn. Àpẹẹrẹ kan lohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tí ọkùnrin kan “tí ẹ̀tẹ̀ bò” lọ bá Jésù láàárín èrò. (Lúùkù 5:12) Nígbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, Òfin Jèhófà sọ pé ẹ̀yìn ibùdó ni káwọn adẹ́tẹ̀ máa gbé, kí wọ́n má bàa kó àrùn náà ran àwọn èèyàn. (Nọ́ńbà 5:1-4) Àmọ́ nígbà tó yá, àwọn aṣáájú ẹ̀sìn gbé òfin tiwọn kalẹ̀ nípa àwọn tó ní àrùn ẹ̀tẹ̀, òfin náà le gan-an, kì í sì í jẹ́ káwọn èèyàn ṣàánú àwọn adẹ́tẹ̀. a Àmọ́ kíyè sí ohun tí Jésù ṣe nígbà tí adẹ́tẹ̀ náà wá bá a. Bíbélì sọ pé: “Bákan náà, adẹ́tẹ̀ kan wá bá a, ó ń bẹ̀ ẹ́, àní lórí ìkúnlẹ̀, ó sọ fún un pé: ‘Tí o bá ṣáà ti fẹ́, o lè jẹ́ kí n mọ́.’ Àánú rẹ̀ wá ṣe é, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fọwọ́ kàn án, ó wá sọ fún un pé: ‘Mo fẹ́ bẹ́ẹ̀! Kí o mọ́.’ Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ẹ̀tẹ̀ náà pòórá lára rẹ̀.” (Máàkù 1:40-42) Jésù mọ̀ pé kò bófin mu rárá bí adẹ́tẹ̀ yẹn ṣe wà láàárín èrò. Síbẹ̀, dípò tí Jésù á fi lé e dà nù, àánú rẹ̀ ṣe Jésù débi pé ó ṣe nǹkan kan tó jọni lójú gan-an. Jésù fọwọ́ kàn án!

12 Wo bó ṣe máa rí lára adẹ́tẹ̀ yẹn nígbà tí Jésù fọwọ́ kàn án! Ká lè mọ bó ṣe rí lára adẹ́tẹ̀ náà, ẹ jẹ́ ká wo ohun tó ṣẹlẹ̀ ṣẹ́nì kan. Dókítà Paul Brand, tó jẹ́ onímọ̀ nípa àrùn ẹ̀tẹ̀ sọ ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tó ń tọ́jú adẹ́tẹ̀ kan lórílẹ̀-èdè Íńdíà. Bí dókítà yẹn ṣe ń ṣàyẹ̀wò adẹ́tẹ̀ náà, ó gbọ́wọ́ lé e léjìká, ó sì ní kí ògbufọ̀ kan bá òun ṣàlàyé ọ̀nà tóun fẹ́ gbà tọ́jú rẹ̀ fún un. Ni adẹ́tẹ̀ náà bá bú sẹ́kún! Dókítà náà wá béèrè pé: “Àbí mo ṣi ọ̀rọ̀ sọ ni?” Ògbufọ̀ béèrè lọ́wọ́ ọ̀dọ́kùnrin náà lédè rẹ̀, ó sì fèsì pé: “Rárá o, dókítà. Ó sọ pé ohun tó ń pa òun lẹ́kún ni pé dókítà náà gbé ọwọ́ lé òun léjìká. Ó fi kún un pé kó tó di pé òun wá sọ́dọ̀ dókítà náà, kò sẹ́nì kankan tó ti fọwọ́ kan òun fún ọ̀pọ̀ ọdún.” Ó dájú pé inú adẹ́tẹ̀ tó lọ bá Jésù yẹn máa dùn gan-an nígbà tí Jésù fọwọ́ kàn án, ìyẹn á sì mú kára tù ú. Àmọ́, ohun tí Jésù ṣe fún un tún jùyẹn lọ! Lẹ́yìn tí Jésù fọwọ́ kàn án lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo yẹn, àìsàn burúkú tó ń ṣe é yẹn lọ, ó wá láǹfààní láti pa dà wà pẹ̀lú àwọn mọ̀lẹ́bí ẹ̀, ó sì tún ṣeé ṣe fún un láti máa sin Jèhófà pẹ̀lú wọn!

13, 14. (a) Àwọn wo ni Jésù pàdé bó ṣe fẹ́ wọ ìlú Náínì, kí sì nìdí tí ohun tó ṣẹlẹ̀ náà fi bani nínú jẹ́ gan-an? (b) Nígbà tí àánú opó Náínì ṣe Jésù, kí ni Jésù ṣe fún un?

13 Jésù máa ń ran àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ lọ́wọ́ torí pé ó jẹ́ aláàánú. Ojú Jésù kì í gbà á tó bá rí i tí ìbànújẹ́ dorí àwọn èèyàn kodò. Bí àpẹẹrẹ, jẹ́ ká wo ìtàn tó wà nínú Lúùkù 7:11-15. Ìtòsí ìlú Náínì ní ìpínlẹ̀ Gálílì lọ̀rọ̀ náà ti ṣẹlẹ̀, Jésù sì ti lo nǹkan bí ọdún kan àti oṣù mẹ́sàn-án lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ nígbà yẹn. Bí Jésù ṣe ń sún mọ́ ẹnubodè ìlú náà, ó pàdé àwọn èèyàn tí wọ́n fẹ́ lọ sin òkú ọ̀dọ́kùnrin kan. Òkú ọ̀fọ̀ ni òkú ọmọ yìí, torí òun nìkan ni ìyá ẹ̀ bí, opó sì ni ìyá náà. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìgbà kejì rèé tí ìyá ọmọ náà máa bára ẹ̀ nípò yìí. Àkọ́kọ́ ni ìgbà tọ́kọ ẹ̀ kú. Àmọ́ ọmọ ẹ̀ ni lọ́tẹ̀ yìí, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ọmọ yìí nìkan ló ń gbọ́ bùkátà ẹ̀. Ó ṣeé ṣe káwọn tó ń sunkún àtàwọn tó ń kọrin arò wà lára àwọn èrò tó ń tẹ̀ lé ìyá ọmọ náà. (Jeremáyà 9:17, 18; Mátíù 9:23) Àmọ́ obìnrin tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ náà ni Jésù tẹjú mọ́, torí ó ní láti jẹ́ pé ẹ̀gbẹ́ àwọn tó gbé òkú ọmọ náà ló ti ń rìn.

14 Bí Jésù ṣe ń wo obìnrin tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ náà “àánú rẹ̀ ṣe é.” Ó wá fi ohùn tó tura sọ fún un pé: “Má sunkún mọ́.” Lẹ́yìn náà, Jésù sún mọ́ ohun tí wọ́n fi gbé òkú náà, ó sì fọwọ́ kàn án. Làwọn tó gbé òkú náà bá dúró, ó sì ṣeé ṣe kíyẹn mú káwọn èrò tó ń tẹ̀ lé wọn náà dúró. Jésù wá pàṣẹ fún òkú náà pé: “Ọ̀dọ́kùnrin, mo sọ fún ọ, dìde!” Kí ló ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn náà? ‘Ọkùnrin tó ti kú náà wá dìde jókòó, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ̀rọ̀’ àfi bí ẹni tó jí lójú oorun! Ohun tí Bíbélì sọ lẹ́yìn náà wọni lọ́kàn gan-an, ó ní: “Jésù sì fà á lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́.”

15. (a) Bá a ṣe rí i nínú ìtàn Bíbélì nípa bí Jésù ṣe máa ń ṣàánú àwọn èèyàn, kí ló yẹ kẹ́nì kan ṣe lẹ́yìn tí àánú àwọn èèyàn bá ṣe é? (b) Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù?

15 Kí la rí kọ́ nínú àwọn ìtàn yìí? Kíyè sí i pé ọ̀kọ̀ọ̀kan ìtàn yẹn ló jẹ́ ká rí i pé tí Jésù bá rí àwọn tí ìyà ń jẹ, kì í ṣe pé àánú wọn máa ń ṣe é nìkan, ó tún máa ń rí i dájú pé òun ṣe ohun kan láti ràn wọ́n lọ́wọ́. Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù? Ọlọ́run ti fún àwa Kristẹni ní iṣẹ́ pàtàkì kan pé ká wàásù ìhìn rere, ká sì sọ àwọn èèyàn di ọmọ ẹ̀yìn. Òótọ́ ni pé ìfẹ́ tá a ní fún Ọlọ́run ni olórí ìdí tá a fi ń ṣe iṣẹ́ náà. Àmọ́, ó tún yẹ ká fi sọ́kàn pé ó ṣe pàtàkì kí àánú àwọn èèyàn máa ṣe wá ká tó lè ṣe iṣẹ́ náà láṣeyọrí. Tí àánú àwọn èèyàn bá ń ṣe wá bíi ti Jésù, a máa ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti wàásù ìhìn rere fún wọn. (Mátíù 22:37-39) Yàtọ̀ síyẹn, táwọn tá a jọ ń sin Jèhófà bá ń jìyà tàbí tí wọ́n ń ṣọ̀fọ̀ torí èèyàn wọn tó kú, kí la lè ṣe láti fi hàn pé àánú wọn ń ṣe wá? Àwa ò lè ṣe iṣẹ́ ìyanu láti yanjú ìṣòro wọn, a ò sì lè jí èèyàn wọn tó kú dìde. Àmọ́, a lè fàánú hàn sí wọn tá a bá ń ṣaájò wọn, tá a sì ń ṣe ohun kan láti ràn wọ́n lọ́wọ́.​—Éfésù 4:32.

“Baba, Dárí Jì Wọ́n”

16. Kí ni Jésù ṣe tó fi hàn pé ó ṣe tán láti dárí jini, kódà nígbà tó wà lórí òpó igi oró?

16 Ọ̀nà míì tún wà tí Jésù gbà fìfẹ́ hàn lọ́nà tó pé bíi ti Bàbá rẹ̀, ìyẹn ni bí òun náà ṣe “ṣe tán láti dárí jini.” (Sáàmù 86:5) Kódà, ó ṣì fi hàn pé òun ṣe tán láti dárí jini nígbà tó wà lórí òpó igi oró. Rò ó wò ná: Kí ni Jésù sọ nígbà táwọn èèyàn fẹ́ pa á ní ìpa ìkà, tó sì ń jẹ̀rora bí wọ́n ṣe kànṣó mọ́ ọn lọ́wọ́ lẹ́sẹ̀? Ṣé ńṣe ló bẹ̀rẹ̀ sí í ké pe Jèhófà pé kó fìyà jẹ àwọn tó fẹ́ pa òun? Rárá o. Kàkà bẹ́ẹ̀, lára ọ̀rọ̀ tó sọ kó tó kú ni pé: “Baba, dárí jì wọ́n, torí wọn ò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.”​—Lúùkù 23:34. b

17-19. Láìka bí àpọ́sítélì Pétérù ṣe ṣẹ́ Jésù lẹ́ẹ̀mẹta, àwọn nǹkan wo ni Jésù ṣe tó fi hàn pé ó ti dárí jì í?

17 A tún rí àpẹẹrẹ míì tó wọni lọ́kàn nípa bí Jésù ṣe ń dárí jini látinú ohun tó ṣe nígbà tí àpọ́sítélì Pétérù sẹ́ ẹ. Òótọ́ kan ni pé Pétérù nífẹ̀ẹ́ Jésù gan-an. Ní alẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá, oṣù Nísàn, ìyẹn alẹ́ tó ṣáájú ikú Jésù, Pétérù sọ fún un pé: “Olúwa, mo ṣe tán láti bá ọ lọ sẹ́wọ̀n, kí n sì bá ọ kú.” Àmọ́ ní wákàtí díẹ̀ lẹ́yìn náà, ẹ̀ẹ̀mẹta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni Pétérù sẹ́ Jésù, tó lóun ò tiẹ̀ mọ̀ ọ́n rí! Bíbélì sọ ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tí Pétérù sẹ́ Jésù lẹ́ẹ̀kẹta. Bíbélì sọ pé: “Olúwa . . . yíjú pa dà, ó sì wo Pétérù tààràtà.” Nígbà tí Pétérù rí i pé ẹ̀ṣẹ̀ ńlá lòun dá bóun ṣe sẹ́ Jésù, ẹ̀dùn ọkàn bá a, torí náà ó “bọ́ síta, ó sì sunkún gidigidi.” Lẹ́yìn tí Jésù kú lọ́jọ́ yẹn, ó ṣeé ṣe kí Pétérù máa bi ara ẹ̀ pé, ‘Ṣé Olúwa mi dárí jì mí báyìí?’​—Lúùkù 22:33, 61, 62.

18 Kò pẹ́ tí Pétérù fi rí ìdáhùn ìbéèrè yẹn. Àárọ̀ ọjọ́ kẹrìndínlógún, oṣù Nísàn ni Jésù jíǹde, ó sì jọ pé ọjọ́ yẹn gan-an ló fara han Pétérù. (Lúùkù 24:34; 1 Kọ́ríńtì 15:4-8) Láìka bí Pétérù ṣe sẹ́ Jésù kanlẹ̀, kí nìdí tí Jésù fi rí i pé òun wáyè bá a sọ̀rọ̀? Jésù mọ̀ pé Pétérù ti ronú pìwà dà, torí náà ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ńṣe ni Jésù fẹ́ kó mọ̀ pé òun ṣì nífẹ̀ẹ́ ẹ̀ àti pé òun ṣì mọyì ẹ̀. Àmọ́ Jésù tún ṣe ohun míì tó jẹ́ kí ọkàn Pétérù balẹ̀.

19 Ní àkókò kan lẹ́yìn náà, Jésù fara han àwọn ọmọ ẹ̀yìn létí Òkun Gálílì. Lọ́jọ́ yẹn, ẹ̀ẹ̀mẹta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni Jésù bi Pétérù (ẹni tó sẹ́ ẹ lẹ́ẹ̀mẹta) bóyá ó nífẹ̀ẹ́ òun. Nígbà tó bi í lẹ́ẹ̀kẹta, Pétérù fèsì pé: “Olúwa, o mọ ohun gbogbo; o mọ̀ pé mo ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ọ.” Ká sòótọ́, Jésù mọ̀ pé Pétérù nífẹ̀ẹ́ òun, torí ó mọ ohun tó wà lọ́kàn rẹ̀. Síbẹ̀, Jésù fẹ́ kí Pétérù fẹnu ara rẹ̀ sọ ọ́ jáde. Bákan náà, Jésù sọ fún Pétérù pé kó ‘máa bọ́ àwọn àgùntàn òun kéékèèké,’ kó sì “máa bójú tó” wọn. (Jòhánù 21:15-17) Ṣáájú àkókò yẹn, Jésù ti ní kí Pétérù máa wàásù. (Lúùkù 5:10) Àmọ́ lọ́tẹ̀ yìí, kí Pétérù lè mọ̀ pé Jésù fọkàn tán òun, Jésù fún un ní iṣẹ́ pàtàkì míì, ó ní kó máa bójú tó àwọn tó máa di ọmọlẹ́yìn òun. Láìpẹ́ sígbà yẹn, Jésù lo Pétérù láti kó ipa pàtàkì nínú iṣẹ́ táwọn ọmọ ẹ̀yìn ṣe. (Ìṣe 2:1-41) Ó dájú pé ọkàn Pétérù máa balẹ̀ gan-an nígbà tó rí ẹ̀rí tó fi hàn pé Jésù ti dárí ji òun àti pé ó ṣì fọkàn tán òun!

Ṣé O “Mọ Ìfẹ́ Kristi”?

20, 21. Báwo la ṣe lè “mọ ìfẹ́ Kristi” dáadáa?

20 Ní tòótọ́, ọ̀nà tó dáa gan-an ni Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gbà ṣàpèjúwe ìfẹ́ Kristi. Àmọ́ tá a bá ronú nípa ìfẹ́ tí Jésù fi hàn, kí ló yẹ ká ṣe? Bíbélì rọ̀ wá pé ká “mọ ìfẹ́ Kristi tó ré kọjá ìmọ̀.” (Éfésù 3:19) Lóòótọ́, àwọn Ìwé Ìhìn Rere tó sọ̀rọ̀ nípa ìgbésí ayé àti iṣẹ́ òjíṣẹ́ Jésù ti jẹ́ ká mọ ọ̀pọ̀ nǹkan nípa ìfẹ́ tí Kristi fi hàn. Àmọ́, ká tó lè “mọ ìfẹ́ Kristi” dáadáa, a gbọ́dọ̀ ṣe ju ká kàn mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa rẹ̀.

21 Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a tú sí “mọ̀” túmọ̀ sí kéèyàn mọ nǹkan “nípasẹ̀ àwọn nǹkan tóun fúnra ẹ̀ ń ṣe.” Tá a bá ń lo okun àti àkókò wa láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́, tá à ń ṣàánú wọn nígbà ìṣòro, tá a sì ń dárí jì wọ́n látọkàn wá, a máa fi hàn pé à ń fara wé Jésù, a sì mọ bí nǹkan ṣe ń rí lára ẹ̀. Ìgbà tá a bá ń ṣe àwọn nǹkan yìí la tó lè sọ pé a “mọ ìfẹ́ Kristi tó ré kọjá ìmọ̀.” Ká má gbàgbé pé bá a bá ṣe túbọ̀ ń fara wé Kristi, bẹ́ẹ̀ làá túbọ̀ máa sún mọ́ Jèhófà, Ọlọ́run wa onífẹ̀ẹ́, ẹni tí Jésù fìwà jọ lọ́nà tó pé.

a Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn ṣòfin pé, ó kéré tán èèyàn gbọ́dọ̀ jìnnà sí adẹ́tẹ̀ tó ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin (nǹkan bíi mítà méjì). Àmọ́ tí afẹ́fẹ́ bá ń fẹ́, adẹ́tẹ̀ náà gbọ́dọ̀ jìnnà tó, ó kéré tán, ọgọ́rùn-ún ìgbọ̀nwọ́ (nǹkan bíi mítà márùndínláàádọ́ta) síbi téèyàn bá wà. Ìwé Midrash Rabbah sọ̀rọ̀ nípa rábì kan tó ń fara pa mọ́ fáwọn adẹ́tẹ̀ àti rábì míì tó ń sọ àwọn adẹ́tẹ̀ lókùúta, láti fi lé wọn dà nù. Torí náà, kì í ṣe ohun tuntun sáwọn adẹ́tẹ̀ táwọn èèyàn bá kórìíra wọn, tí wọ́n sì ń fojú àbùkù wò wọ́n.

b Àwọn ìwé àfọwọ́kọ àtijọ́ kan yọ ọ̀rọ̀ yìí kúrò nínú Lúùkù 23:34. Àmọ́, ó wà nínú ọ̀pọ̀ ìwé àfọwọ́kọ míì tó ṣeé gbára lé, torí náà a ò yọ ọ́ nínú Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun, ó sì tún wà nínú ọ̀pọ̀ ìtumọ̀ Bíbélì míì. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àwọn ọmọ ogun Róòmù tó kan Jésù mọ́gi ni Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ ọ̀rọ̀ yìí. Ká sòótọ́, wọn ò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe, torí wọn ò mọ ẹni tí Jésù jẹ́ gan-an. Ó tún ṣeé ṣe káwọn Júù tó ní kí wọ́n pa Jésù wà lára àwọn tí Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ ọ̀rọ̀ yẹn, torí àwọn kan lára wọn ronú pìwà dà nígbà tó yá. (Ìṣe 2:36-38) Àmọ́, àwọn aṣáájú ẹ̀sìn jẹ̀bi ní tiwọn, torí bó tiẹ̀ jẹ́ pé wọ́n mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run ni Jésù, wọ́n fúngun mọ́ àwọn ará Róòmù pé kí wọ́n pa á. Torí náà, Ọlọ́run ò lè dárí ji ọ̀pọ̀ lára wọn.​—Jòhánù 11:45-53.