Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORÍ 20

“Ọlọ́gbọ́n Ni”​—Síbẹ̀ Ó Jẹ́ Onírẹ̀lẹ̀

“Ọlọ́gbọ́n Ni”​—Síbẹ̀ Ó Jẹ́ Onírẹ̀lẹ̀

1-3. Kí ló mú kó dá wa lójú pé Jèhófà jẹ́ onírẹ̀lẹ̀?

 BÀBÁ kan fẹ́ kọ́ ọmọ ẹ̀ kékeré ní ẹ̀kọ́ pàtàkì kan, ó sì fẹ́ kí ẹ̀kọ́ yìí wọ̀ ọ́ lọ́kàn dáadáa. Kí ló yẹ kó ṣe? Ṣé kó dúró sẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀, kó sì máa pariwo mọ́ ọn ni? Àbí kó bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ kí ọmọ náà lè rójú ẹ̀ dáadáa, kó sì bá ọmọ náà sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́? Ó dájú pé ńṣe ni bàbá tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n, tó sì lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ máa bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ táá sì bá ọmọ náà sọ̀rọ̀ lọ́nà pẹ̀lẹ́.

2 Irú Bàbá wo ni Jèhófà jẹ́? Ṣé agbéraga ni àbí onírẹ̀lẹ̀, ṣé ẹni tó ń kanra ni àbí oníwà pẹ̀lẹ́? Jèhófà mọ ohun gbogbo, òun ló sì gbọ́n jù. Àmọ́, àwọn èèyàn tó ní ìmọ̀ tó sì ní làákàyè kì í sábà lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀. Ó ṣe tán Bíbélì sọ pé, “Ìmọ̀ máa ń gbéra ga.” (1 Kọ́ríńtì 3:19; 8:1) Ní ti Jèhófà, “ọlọ́gbọ́n ni,” ó sì tún jẹ́ onírẹ̀lẹ̀. (Jóòbù 9:4) Èyí fi hàn pé bó tiẹ̀ jẹ́ pé Jèhófà ló ga jù lọ láyé àti lọ́run, kò lẹ́mìí ìgbéraga rárá. Báwo la ṣe mọ̀ bẹ́ẹ̀?

3 Jèhófà jẹ́ mímọ́, torí náà kò ní ìwà burúkú èyíkéyìí bí ìgbéraga tó máa ń sọni di ẹlẹ́gbin. (Máàkù 7:20-22) Kíyè sí ohun tí wòlíì Jeremáyà sọ fún Jèhófà, ó ní: “Ó dájú pé o máa rántí, wàá sì bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ kí o lè ràn mí lọ́wọ́.” a (Ìdárò 3:20) Àbẹ́ ò rí nǹkan! Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ ayé àtọ̀run ṣe tán láti “bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀,” tàbí rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ sí ipò rírẹlẹ̀ tí Jeremáyà wà, kó lè ràn án lọ́wọ́. (Sáàmù 113:7) Jèhófà mà nírẹ̀lẹ̀ o! Àmọ́ báwo ló ṣe ń fi hàn pé òun jẹ́ onírẹ̀lẹ̀? Báwo ni ọgbọ́n ṣe ń hàn nínú ìwà ìrẹ̀lẹ̀ Jèhófà? Báwo ló sì ṣe ń ṣe wá láǹfààní?

Bí Jèhófà Ṣe Ń Fi Hàn Pé Òun Jẹ́ Onírẹ̀lẹ̀

4, 5. (a) Kí ló túmọ̀ sí láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, àwọn ìwà wo ló máa fi hàn pé ẹnì kan jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, èrò wo ni kò sì yẹ ká ní nípa ìwà ìrẹ̀lẹ̀? (b) Báwo ni Jèhófà ṣe fi hàn pé òun níwà ìrẹ̀lẹ̀ nínú àjọṣe ẹ̀ pẹ̀lú Dáfídì, báwo sì ni ìwà ìrẹ̀lẹ̀ Jèhófà ṣe ṣe wá láǹfààní?

4 Ẹni tó bá jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ kì í gbéra ga, bẹ́ẹ̀ ni kì í ro ara ẹ̀ ju bó ṣe yẹ lọ. Ó máa ń ní ìwà tútù, sùúrù àti ìgbatẹnirò. (Gálátíà 5:22, 23) Àmọ́ o, ká má rò ó láé pé ìwà ìrẹ̀lẹ̀, ìwà tútù àti sùúrù Jèhófà máa jẹ́ kó gbójú fo ìwà ìrẹ́jẹ táwọn èèyàn ń hù tàbí kẹ́rù máa bà á láti lo agbára ìparun rẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni ìwà ìrẹ̀lẹ̀ àti ìwà tútù Jèhófà ń fi hàn pé ó máa ń lo agbára ẹ̀ lọ́nà tó tọ́, ó sì máa ń kó ara ẹ̀ níjàánu. (Àìsáyà 42:14) Bákan náà, bí Jèhófà ṣe jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ fi hàn pé ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n. Ìwé kan tó ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé: “Paríparí ohun tá a tú ìrẹ̀lẹ̀ sí ni . . . pé ó jẹ́ àìjọra-ẹni-lójú àti pé ó jẹ́ ìpìlẹ̀ pàtàkì fún gbogbo ọgbọ́n.” Torí náà, èèyàn ò lè ní ọgbọ́n tòótọ́ àfi tó bá jẹ́ onírẹ̀lẹ̀. Báwo ni ìwà ìrẹ̀lẹ̀ Jèhófà ṣe ń ṣe wá láǹfààní?

Ńṣe ni bàbá tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n, tó sì jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ máa ń bá àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́

5 Ọba Dáfídì kọrin sí Jèhófà pé: “O fún mi ní apata rẹ láti gbà mí là, ọwọ́ ọ̀tún rẹ ń tì mí lẹ́yìn, ìrẹ̀lẹ̀ rẹ sì sọ mí di ẹni ńlá.” (Sáàmù 18:35) Ńṣe ló dà bíi pé Jèhófà bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ kó lè sún mọ́ Dáfídì, kó lè dáàbò bò ó, kó sì máa tọ́jú ẹ̀ lójoojúmọ́ bó tiẹ̀ jẹ́ pé aláìpé ni. Dáfídì mọ̀ pé tí Jèhófà bá mọ̀ọ́mọ̀ rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀ láti ran òun lọ́wọ́ nìkan ló máa jẹ́ kóun borí àwọn ọ̀tá òun, kóun sì di ọba tó lókìkí. Bọ́rọ̀ tiwa náà ṣe rí nìyẹn. Torí pé Jèhófà Bàbá wa onífẹ̀ẹ́ àti oníwà pẹ̀lẹ́ rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀ tó sì ràn wá lọ́wọ́ ló jẹ́ ká nírètí pé a lè rí ìgbàlà.

6, 7. (a) Kí nìdí tí Bíbélì ò fi sọ ọ́ níbì kankan pé Jèhófà mọ̀wọ̀n ara ẹ̀? (b) Báwo ni ìwà tútù àti ọgbọ́n ṣe tan mọ́ra, ta ló sì fi àpẹẹrẹ tó dáa jù lélẹ̀?

6 Ó yẹ ká mọ̀ pé kéèyàn jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti kéèyàn mọ̀wọ̀n ara ẹ̀ yàtọ̀ síra. Ọ̀kan lára àwọn ìwà rere tó yẹ káwọn olóòótọ́ èèyàn ní ni pé kí wọ́n mọ̀wọ̀n ara wọn. Bíi ti ẹni tó jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, ẹni tó mọ̀wọ̀n ara ẹ̀ máa ń ní ọgbọ́n. Bí àpẹẹrẹ, Òwe 11:2 sọ pé: “Ọgbọ́n wà lọ́dọ̀ àwọn tí wọ́n mọ̀wọ̀n ara wọn.” Àmọ́, kò sí ìgbà kankan tí Bíbélì sọ pé Jèhófà mọ̀wọ̀n ara ẹ̀. Kí nìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé tí Bíbélì bá sọ pé ẹnì kan mọ̀wọ̀n ara ẹ̀, ẹni náà mọ̀ pé àwọn ohun kan wà tóun ò lè ṣe. Àmọ́ kò sí ohun tí Olódùmarè ò lè ṣe àfi ohun tó bá fúnra ẹ̀ pinnu pé òun ò ní ṣe torí àwọn ìlànà òdodo rẹ̀. (Máàkù 10:27; Títù 1:2) Yàtọ̀ síyẹn, Jèhófà ni Ẹni Gíga Jù Lọ, kò sí lábẹ́ ẹnikẹ́ni. Torí náà, a ò lè retí pé kó mọ̀wọ̀n ara ẹ̀.

7 Síbẹ̀, onírẹ̀lẹ̀ ni Jèhófà, ó sì níwà tútù. Ó kọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé tí wọ́n bá fẹ́ ní ọgbọ́n tòótọ́, wọ́n gbọ́dọ̀ jẹ́ oníwà tútù. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ sọ nípa ẹni tó “fi ìwà tútù ṣe àwọn iṣẹ́ tó fi hàn pé ó gbọ́n.” b (Jémíìsì 3:13) Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ Jèhófà.

Jèhófà Máa Ń Fa Iṣẹ́ Léni Lọ́wọ́ Ó sì Ń Fetí Síni

8-10. (a) Kí nìdí tó fi yani lẹ́nu pé Jèhófà máa ń fa iṣẹ́ lé àwọn míì lọ́wọ́ tó sì máa ń tẹ́tí sí wọn? (b) Kí ni Olódùmarè ṣe fáwọn áńgẹ́lì tó fi hàn pé ó jẹ́ onírẹ̀lẹ̀?

8 Ẹ̀rí kan tó wúni lórí tó fi hàn pé Jèhófà nírẹ̀lẹ̀ ni pé ó máa ń fa iṣẹ́ lé àwọn míì lọ́wọ́, ó sì máa ń tẹ́tí sí wọn. Ó yani lẹ́nu gan-an pé Jèhófà tiẹ̀ máa ń tẹ́tí sáwọn míì torí pé kò nílò ìrànlọ́wọ́ tàbí ìmọ̀ràn ẹnikẹ́ni. (Àìsáyà 40:13, 14; Róòmù 11:34, 35) Síbẹ̀, ọ̀pọ̀ ìgbà ni Bíbélì jẹ́ ká rí i pé Jèhófà máa ń ṣe bẹ́ẹ̀ torí pé onírẹ̀lẹ̀ ni.

9 Bí àpẹẹrẹ, wo ohun pàtàkì kan tó ṣẹlẹ̀ nígbà ayé Ábúráhámù. Ìgbà kan wà tí Ábúráhámù gba àlejò mẹ́ta, ó pe ọ̀kan nínú wọn ní “Jèhófà.” Áńgẹ́lì làwọn àlejò mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yẹn, àmọ́ ńṣe ni ọ̀kan nínú wọn wá lórúkọ Jèhófà, orúkọ Jèhófà ló sì fi ń ṣe ohun tó ń ṣe. Torí náà, tí áńgẹ́lì yẹn bá sọ̀rọ̀ tàbí tó ṣe nǹkan kan, Jèhófà ló sọ ọ́ tó sì ṣe é. Jèhófà ní kí áńgẹ́lì náà sọ fún Ábúráhámù pé òun ti gbọ́ “igbe àwọn tó ń ráhùn nípa Sódómù àti Gòmórà.” Jèhófà wá sọ pé: “Èmi yóò lọ wò ó bóyá ohun tí mò ń gbọ́ nípa wọn náà ni wọ́n ń ṣe. Tí kò bá sì rí bẹ́ẹ̀, màá lè mọ̀.” (Jẹ́nẹ́sísì 18:3, 20, 21) A mọ̀ pé èyí ò túmọ̀ sí pé Olódùmarè fúnra ẹ̀ máa sọ̀ kalẹ̀ “lọ wò ó.” Kàkà bẹ́ẹ̀, àwọn áńgẹ́lì ló tún rán láti lọ wo nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 19:1) Kí nìdí? Ṣé Jèhófà tó ń rí ohun gbogbo kò “lè mọ” ohun tó ń ṣẹlẹ̀ gangan lágbègbè yẹn láìjẹ́ pé ó kọ́kọ́ rán àwọn áńgẹ́lì ni? Ó dájú pé ó lè mọ̀ ọ́n. Àmọ́ torí pé Jèhófà jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, ó fa iṣẹ́ náà lé àwọn áńgẹ́lì lọ́wọ́ pé kí wọ́n lọ wádìí ọ̀rọ̀ náà, kí wọ́n sì bẹ Lọ́ọ̀tì àti ìdílé rẹ̀ wò ní Sódómù.

10 Bákan náà, Jèhófà máa ń tẹ́tí sáwọn míì. Nígbà kan, ó ní káwọn áńgẹ́lì òun wá sọ oríṣiríṣi ọ̀nà tí wọ́n fi lè mú kí Ọba Áhábù lọ sójú ogun kó sì kú. Lóòótọ́, Jèhófà ò nílò irú ìrànlọ́wọ́ bẹ́ẹ̀. Síbẹ̀, ó gba àbá ọ̀kan nínú àwọn áńgẹ́lì yẹn, ó sì ní kí áńgẹ́lì náà rí i pé ó di ṣíṣe. (1 Àwọn Ọba 22:19-22) Ká sòótọ́, Jèhófà mà níwà ìrẹ̀lẹ̀ o!

11, 12. Báwo ni Ábúráhámù ṣe rí i pé Jèhófà nírẹ̀lẹ̀?

11 Jèhófà tiẹ̀ ṣe tán láti tẹ́tí sáwa èèyàn aláìpé tá a bá fẹ́ sọ ẹ̀dùn ọkàn wa fún un. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí Jèhófà kọ́kọ́ sọ fún Ábúráhámù pé òun fẹ́ pa Sódómù àti Gòmórà run, ọ̀rọ̀ náà yà á lẹ́nu. Ábúráhámù sọ pé: “Ó dájú pé o ò ní ṣe bẹ́ẹ̀. Ṣé Onídàájọ́ gbogbo ayé kò ní ṣe ohun tó tọ́ ni?” Ó wá bi Jèhófà bóyá ó máa dá àwọn ìlú yẹn sí tó bá rí àádọ́ta olódodo níbẹ̀. Jèhófà fi í lọ́kàn balẹ̀ pé òun máa dá wọn sí. Àmọ́ Ábúráhámù tún bi Jèhófà bóyá ó ṣì máa dá àwọn ìlú náà sí tíye wọn ò bá tiẹ̀ tó bẹ́ẹ̀, tó jẹ́ márùndínláàádọ́ta, ogójì, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Jèhófà ń fi Ábúráhámù lọ́kàn balẹ̀ pé òun máa ṣe ohun tó tọ́, ó ṣì ń bi Jèhófà ní ìbéèrè kan náà. Ó ṣeé ṣe kí Ábúráhámù má mọ bí Jèhófà ṣe jẹ́ aláàánú tó nígbà yẹn. Àmọ́ torí pé Jèhófà jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, ó mú sùúrù fún Ábúráhámù, ó sì jẹ́ kó sọ gbogbo nǹkan tó wà lọ́kàn ẹ̀.​—Jẹ́nẹ́sísì 18:23-33.

12 Ọ̀pọ̀ lára àwọn tí orí wọn pé gan-an ni kì í fi sùúrù tẹ́tí sí àwọn tí kò lóye tó wọn. c Àmọ́, ohun tí Jèhófà ṣe nìyẹn. Ẹ ò rí i pé ìwà ìrẹ̀lẹ̀ Ọlọ́run wa pọ̀ gan-an ni! Nígbà tí Jèhófà àti Ábúráhámù jọ ń sọ̀rọ̀, Ábúráhámù tún rí i pé Jèhófà “kì í tètè bínú.” (Ẹ́kísódù 34:6) Ó jọ pé Ábúráhámù wá rí i pé kò yẹ kóun ronú pé Ẹni Gíga Jù Lọ máa ṣe ohun tí kò tọ́. Ìyẹn ló jẹ́ kó bẹ̀bẹ̀ lẹ́ẹ̀mejì pé: “Jèhófà jọ̀ọ́, má bínú sí mi.” (Jẹ́nẹ́sísì 18:30, 32) Jèhófà ò sì bínú sí i ní tòótọ́. Èyí fi hàn pé Jèhófà ní “ìwà tútù . . . tó fi hàn pé ó gbọ́n.”

Jèhófà Máa Ń Fòye Báni Lò

13. Bó ṣe wà nínú Bíbélì, kí ni ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ náà “fòye báni lò,” kí sì nìdí tó fi dáa láti fi ọ̀rọ̀ yìí sọ irú ẹni tí Jèhófà jẹ́?

13 Ohun míì tó tún jẹ́ ká rí i pé Jèhófà jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ni pé ó máa ń fòye báni lò. Àmọ́, àwa èèyàn aláìpé kì í sábà fòye báni lò, ìyẹn ò sì dáa rárá. A ti kẹ́kọ̀ọ́ pé Jèhófà máa ń tẹ́tí sáwọn èèyàn àtàwọn áńgẹ́lì tí wọ́n bá ń sọ èrò wọn. Ó tún máa ń gbà láti ṣe ohun tí wọ́n bá sọ, tí kò bá ti ta ko àwọn ìlànà òdodo rẹ̀. Nínú Bíbélì, ọ̀rọ̀ náà “fòye báni lò” túmọ̀ sí pé kéèyàn “má ṣe rin kinkin mọ́ èrò ara ẹ̀.” Bí Jèhófà ṣe jẹ́ ẹni tó ń fòye báni lò tún jẹ́ ẹ̀rí míì pé ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n. Jémíìsì 3:17 sọ pé: “Ọgbọ́n tó wá láti òkè . . . ń fòye báni lò.” Ọ̀nà wo ni Jèhófà tó jẹ́ ọba ọgbọ́n gbà ń fòye báni lò? Ọ̀nà pàtàkì kan ni pé ó máa ń yí ìpinnu ẹ̀ pa dà nígbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀. Rántí pé ìtumọ̀ orúkọ Jèhófà ni pé ó lè di ohunkóhun tó bá fẹ́ kó lè ṣe ohun tó bá ní lọ́kàn láti ṣe. (Ẹ́kísódù 3:14) Torí náà, ńṣe ni orúkọ Jèhófà jẹ́ ká mọ̀ pé ó máa ń yí ìpinnu ẹ̀ pa dà nígbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀, ó sì máa ń fòye báni lò.

14, 15. Kí ni ìran tí Ìsíkíẹ́lì rí nípa kẹ̀kẹ́ ẹṣin ọ̀run kọ́ wa nípa apá ti ọ̀run lára ètò Jèhófà, báwo ló sì ṣe yàtọ̀ sí ètò táwọn èèyàn dá sílẹ̀?

14 Àkọsílẹ̀ pàtàkì kan wà nínú Bíbélì tó jẹ́ ká mọ díẹ̀ sí i nípa bí Jèhófà ṣe máa ń yí ìpinnu ẹ̀ pa dà nígbà tó bá yẹ bẹ́ẹ̀. Wòlíì Ìsíkíẹ́lì rí ìran nípa apá ti ọ̀run lára ètò Jèhófà, tó jẹ́ àpapọ̀ àwọn áńgẹ́lì. Ó rí kẹ̀kẹ́ ẹṣin kan tó tóbi gìrìwò, tí Jèhófà fúnra ẹ̀ ń darí nígbà gbogbo. Bó ṣe ń rìn ló gbàfiyèsí jù. Ẹ̀gbẹ́ mẹ́rin ni àwọn àgbá kẹ̀kẹ́ náà ní, ojú sì wà káàkiri lára wọn, ìyẹn mú kí wọ́n lè rí ibi gbogbo, wọ́n sì lè dédé yà lórí ìrìn láìsí pé wọ́n dúró tàbí wọ́n ṣẹ́rí pa dà. Kì í ṣe pé kẹ̀kẹ́ ẹṣin ńlá yìí rọra ń lọ bí ọkọ̀ akẹ́rù tó gbé ẹrù tó pọ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó lè sáré kọjá fìà bíi mànàmáná, kódà ó lè yà bàrá sọ́tùn-ún tàbí sósì lórí eré! (Ìsíkíẹ́lì 1:1, 14-28) Èyí fi hàn pé ètò Jèhófà máa ń ṣe bíi ti Olódùmarè Ọba Aláṣẹ tó ń darí rẹ̀, ní ti pé ètò Jèhófà náà máa ń ṣàwọn àyípadà tó yẹ ní kíá, kó lè bójú tó àwọn nǹkan tó ń fẹ́ àtúnṣe.

15 Tó bá dọ̀rọ̀ pé ká tètè ṣe àyípadà tó yẹ, àwa èèyàn ò lè dà bíi Jèhófà pátápátá. Ohun tó sábà máa ń ṣẹlẹ̀ ni pé, àwọn èèyàn àtàwọn ètò tí wọ́n dá sílẹ̀ kì í tètè ṣe àwọn àyípadà tó bá yẹ, ńṣe ni wọ́n máa ń rin kinkin mọ́ àwọn ìpinnu tí wọ́n ti ṣe. Àpèjúwe kan rèé: Ọkọ̀ òkun ńlá tí wọ́n fi ń gbépo tàbí ọkọ̀ rélùwéè ńlá tí wọ́n fi ń kẹ́rù máa ń jọni lójú gan-an, torí bó ṣe tóbi àti bó ṣe lágbára tó. Àmọ́ tí nǹkan bá ṣẹlẹ̀ lójijì, kì í rọrùn fáwọn ọkọ̀ yìí láti yà sọ́tùn-ún tàbí sósì lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, tí ohun kan bá dí ọ̀nà tí ọkọ̀ rélùwéè ń gbà, ọkọ̀ náà ò lè ṣẹ́rí pa dà rárá, bẹ́ẹ̀ sì ni kò lè dúró lójijì. Tí wọ́n bá tẹ bíréèkì ẹ̀, ó ṣì máa rìn tó nǹkan bíi kìlómítà méjì kó tó lè dúró! Bákan náà, lẹ́yìn tí wọ́n bá paná gbogbo ẹ́ńjìnnì ọkọ̀ òkun tí wọ́n fi ń gbépo, ó ṣì lè rìn tó kìlómítà mẹ́jọ kó tó dúró. Kódà tí wọ́n bá fi ọkọ̀ náà sí rìfáàsì, ó ṣì lè kọ́kọ́ rìn tó kìlómítà mẹ́ta síwájú, kó tó lè pa dà! Bọ́rọ̀ ètò táwọn èèyàn bá ṣe ṣe máa ń rí nìyẹn, torí wọn kì í fòye báni lò, wọ́n sì máa ń rin kinkin mọ́ ìpinnu wọn. Ìgbéraga kì í sábà jẹ́ káwọn èèyàn ṣe àyípadà tó yẹ. Èyí ti mú káwọn ilé iṣẹ́ kan kógbá wọlé, táwọn ìjọba kan sì dojú dé. (Òwe 16:18) A mà dúpẹ́ o pé Jèhófà àti ètò rẹ̀ ò dà bíi wọn!

Jèhófà Máa Ń Fòye Báni Lò

16. Báwo ni Jèhófà ṣe fòye bá Lọ́ọ̀tì lò nígbà tó fẹ́ pa Sódómù àti Gòmórà run?

16 Ẹ jẹ́ ká tún sọ̀rọ̀ nípa ìparun Sódómù àti Gòmórà. Áńgẹ́lì Jèhófà sọ fún Lọ́ọ̀tì àti ìdílé rẹ̀ ní tààràtà pé: “Ẹ sá lọ sí agbègbè olókè.” Ṣùgbọ́n Lọ́ọ̀tì ò fẹ́ lọ síbẹ̀. Ló bá bẹ̀bẹ̀ pé: “Jèhófà jọ̀ọ́, má ṣe jẹ́ kí n lọ síbẹ̀ yẹn!” Lọ́ọ̀tì gbà pé òun máa kú tóun bá sá lọ sórí àwọn òkè, ó wá bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kóun àti ìdílé òun sá lọ sí ìlú kan tí kò jìnnà tó ń jẹ́ Sóárì. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ìlú yẹn wà lára àwọn ìlú tí Jèhófà fẹ́ pa run. Ohun míì tún ni pé kò yẹ kí Lọ́ọ̀tì bẹ̀rù láti sá lọ sórí àwọn òkè náà torí ó dájú pé Jèhófà máa dáàbò bò ó níbẹ̀. Àmọ́, Jèhófà gbọ́ ẹ̀bẹ̀ Lọ́ọ̀tì. Áńgẹ́lì yẹn sọ fún Lọ́ọ̀tì pé: “Ó dáa, màá tún ro tìẹ, mi ò sì ní run ìlú tí o sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí.” (Jẹ́nẹ́sísì 19:17-22) Ẹ ò rí i pé Jèhófà máa ń fòye báni lò gan-an!

17, 18. Báwo ni Jèhófà ṣe fòye bá àwọn ará Nínéfè lò?

17 Aláàánú àti onídàájọ́ òdodo ni Jèhófà. Tó bá rí i pé ẹnì kan ti ronú pìwà dà lóòótọ́, ó máa ṣàánú ẹni náà, á sì dárí jì í. Ẹ jẹ́ ká wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tí Ọlọ́run rán wòlíì Jónà sí Nínéfè. Àwọn èèyàn tó wà nílùú náà burú gan-an, wọ́n sì máa ń hùwà ipá. Nígbà tí Jónà ń lọ káàkiri ìlú náà, ohun tó ń kéde ò ju pé: Ogójì ọjọ́ péré ló kù kí ìlú yìí pa run. Àmọ́, ibi tí Jónà fojú sí ọ̀nà ò gbabẹ̀ torí pé nǹkan yí pa dà pátápátá, àwọn ará Nínéfè ronú pìwà dà!​—Jónà, orí kẹta.

18 Tá a bá ronú lórí ìyàtọ̀ tó wà láàárín ohun tí Jèhófà ṣe nígbà táwọn ará Nínéfè ronú pìwà dà àti ohun tí Jónà ṣe, ẹ̀kọ́ ńlá la máa rí kọ́. Ní ti Jèhófà, dípò kó di “jagunjagun tó lágbára” kó sì pa àwọn ará Nínéfè run, ńṣe ló yí èrò ẹ̀ pa dà tó sì dárí jì wọ́n. d (Ẹ́kísódù 15:3) Àmọ́ Jónà ò fara mọ́ èrò Jèhófà, kò sì fẹ́ fàánú hàn bíi tiẹ̀. Dípò kí Jónà ronú bí Jèhófà ṣe ń ronú, ńṣe lọ̀rọ̀ ẹ̀ dà bí ọkọ̀ rélùwéè ńlá tàbí ọkọ̀ òkun tá a sọ lẹ́ẹ̀kan. Ó ti sọ tẹ́lẹ̀ pé ìlú yẹn máa pa run, ohun tó sì fẹ́ kó ṣẹlẹ̀ gan-an nìyẹn! Àmọ́, Jèhófà kọ́ Jónà pé kó máa ní sùúrù, kó máa fòye báni lò, kó sì máa fàánú hàn. Ó dájú pé ẹ̀kọ́ pàtàkì nìyẹn.​—Jónà, orí 4.

Jèhófà máa ń fòye bá àwa èèyàn lò, ó sì mọ ibi tí agbára wa mọ

19. (a) Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà máa ń gba tàwa èèyàn rò? (b) Báwo ni Òwe 19:17 ṣe jẹ́ ká mọ̀ pé ‘ẹni rere, tó ń gba tẹni rò,’ tó sì tún jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ni Jèhófà?

19 Bákan náà, Jèhófà máa ń fòye bá àwa èèyàn lò ní ti pé kì í sọ pé ká ṣe ohun tó ju agbára wa lọ. Ọba Dáfídì sọ pé: “Ó mọ ẹ̀dá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.” (Sáàmù 103:14) Jèhófà mọ ibi tí agbára wa mọ, ó sì mọ̀ pé aláìpé ni wá. Kódà, ó mọ̀ wá ju àwa fúnra wa lọ. Kì í retí pé ká ṣe ohun tó ju agbára wa lọ rárá. Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn èèyàn kan wà “tó jẹ́ ẹni rere, tó sì ń gba tẹni rò,” àwọn kan sì wà “tó ṣòroó tẹ́ lọ́rùn.” (1 Pétérù 2:18) Àmọ́ ní ti Jèhófà, ẹni rere ni, kò sì ṣòroó tẹ́ lọ́rùn. Òwe 19:17 sọ pé: “Ẹni tó ń ṣojúure sí aláìní, Jèhófà ló ń yá ní nǹkan.” Torí náà, Jèhófà máa ń kíyè sí gbogbo ohun rere tá a bá ń ṣe fáwọn èèyàn, ìyẹn sì fi hàn lóòótọ́ pé ẹni rere àti ẹni tó ń gba tẹni rò ni Jèhófà! Ju gbogbo ẹ̀ lọ, ẹsẹ Bíbélì yìí jẹ́ ká rí i pé Jèhófà tó dá ayé àtọ̀run máa ń wo ara ẹ̀ bí ẹni pé ó jẹ àwọn tó bá ń ṣoore ní gbèsè, tó sì máa rí i dájú pé òun san gbèsè náà. Àbí ẹ ò rí i pé ìrẹ̀lẹ̀ Jèhófà pọ̀ gan-an!

20. Kí ló mú kó dá wa lójú pé Jèhófà ń gbọ́ àdúrà wa àti pé ó ń dáhùn wọn?

20 Jèhófà ò yí pa dà, bó ṣe ń mú sùúrù fáwọn ìránṣẹ́ ẹ̀ tó sì ń gba tiwọn rò nígbà àtijọ́ náà ló ń ṣe sí wa lónìí. Ó máa ń tẹ́tí sí wa tá a bá gbàdúrà sí i, tá a sì ní ìgbàgbọ́. Tí Jèhófà ò bá tiẹ̀ rán áńgẹ́lì sí wa láti bá wa sọ̀rọ̀, ká má rò pé kò gbọ́ àdúrà wa. Ẹ rántí pé nígbà tí Pọ́ọ̀lù sọ fáwọn Kristẹni bíi tiẹ̀ pé kí wọ́n “túbọ̀ máa gbàdúrà” kí wọ́n lè dá òun sílẹ̀ lẹ́wọ̀n, ó fi kún un pé: “Kí n lè tètè pa dà sọ́dọ̀ yín.” (Hébérù 13:18, 19) Ìyẹn jẹ́ ká rí i pé àdúrà wa lè mú kí Jèhófà ṣe ohun tó yàtọ̀ sí ohun tó fẹ́ ṣe!​—Jémíìsì 5:16.

21. (a) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé onírẹ̀lẹ̀ ni Jèhófà, kí ló dá wa lójú nípa rẹ̀? (b) Báwo ló ṣe rí lára ẹ tó o bá ronú nípa bí Jèhófà ṣe jẹ́ onírẹ̀lẹ̀?

21 Òótọ́ ni pé ìwà ìrẹ̀lẹ̀ Jèhófà hàn nínú bó ṣe jẹ́ oníwà tútù, bó ṣe ń fetí síni, tó ní sùúrù, tó sì ń fòye báni lò, síbẹ̀ kì í gbà káwọn èèyàn fojú kéré àwọn ìlànà òdodo rẹ̀. Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn lè máa rò pé ṣe làwọn ń gba tàwọn ọmọ ìjọ wọn rò bí wọ́n ṣe ń sọ ohun táwọn èèyàn fẹ́ gbọ́, tíyẹn sì ń mú kí wọ́n bomi la àwọn ìlànà òdodo Jèhófà. (2 Tímótì 4:3) Àwọn èèyàn sábà máa ń ṣe ohun tí ò dáa, tí wọ́n á sì sọ pé ṣe làwọn ń gba tàwọn míì rò, àmọ́ ìyẹn yàtọ̀ pátápátá sóhun tó túmọ̀ sí láti gba tẹni rò. Ẹni mímọ́ ni Jèhófà, torí náà kò ní ṣe ohun tó lòdì sí ìlànà òdodo rẹ̀ láé. (Léfítíkù 11:44) Ẹ rántí pé bí Jèhófà ṣe jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ló mú kó máa fòye bá wa lò, ìyẹn ló sì mú ká nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ gan-an. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Jèhófà Ọlọ́run lẹni tó gbọ́n jù lọ láyé àtọ̀run, ó ṣì tún jẹ́ onírẹ̀lẹ̀. Ìyẹn mà wúni lórí o! Inú wa dùn gan-an pé a láǹfààní láti sún mọ́ Ọlọ́run yìí, torí pé bó tiẹ̀ tóbi lọ́ba, ó ṣì jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, onísùúrù àti ẹni tó ń fòye báni lò!

a Nígbà àtijọ́, àwọn adàwékọ tó ń jẹ́ Sóférímù yí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yìí pa dà, wọ́n sọ pé Jeremáyà ló bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀, dípò Jèhófà. Wọ́n gbà pé kò bọ́gbọ́n mu láti sọ pé Ọlọ́run “bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀,” tàbí rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀ kó lè ran èèyàn lọ́wọ́. Torí náà, ọ̀pọ̀ ìtumọ̀ Bíbélì ni kò gbé kókó pàtàkì inú ẹsẹ yìí yọ.

b Àwọn ìtúmọ̀ Bíbélì míì pè é ní “ìwà tútù ti ọgbọ́n” àti “ìwà ìrẹ̀lẹ̀ tí ó fi ọgbọ́n hàn.”

c Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé tí ẹnì kan ò bá ní sùúrù, ẹni náà máa jẹ́ agbéraga. (Oníwàásù 7:8) Torí náà, bí Jèhófà ṣe ní sùúrù tún fi hàn pé ó níwà ìrẹ̀lẹ̀.​—2 Pétérù 3:9.

d Sáàmù 86:5 sọ pé Jèhófà jẹ́ “ẹni rere” àti pé ó “ṣe tán láti dárí jini.” Nígbà tí wọ́n ń tú ọ̀rọ̀ inú sáàmù yìí sí èdè Gíríìkì, ọ̀rọ̀ tí wọ́n lò fún “ṣe tán láti dárí jini” ni e·pi·ei·kes.ʹ Ọ̀rọ̀ yìí kan náà ni wọ́n máa ń lò fún kéèyàn “fòye báni lò.”