Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ismail Sen/Anadolu Agency via Getty Images

Ẹ MÁA ṢỌ́NÀ!

Ìmìtìtì Ilẹ̀ Tó Runlé-Rùnnà ní Orílẹ̀-Èdè Tọ́kì àti Síríà​—Kí Ni Bíbélì Sọ?

Ìmìtìtì Ilẹ̀ Tó Runlé-Rùnnà ní Orílẹ̀-Èdè Tọ́kì àti Síríà​—Kí Ni Bíbélì Sọ?

 Ní Monday, February 6, 2023, ìmìtìtì ilẹ̀ kan tó lágbára ṣẹlẹ̀ lórílẹ̀-èdè Tọ́kì àti Síríà.

  •   “Ìmìtìtì ilẹ̀ kan tó lágbára pa ohun tó ju ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún méje (3,700) èèyàn lọ lápá ibi tó pọ̀ jù lórílẹ̀-èdè Tọ́kì àti ní àríwá ìwọ̀ oòrùn Síríà lọ́jọ́ Monday. Òtútù tó lágbára tún mú, ìyẹn sì dá kún ìṣòro ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tó fara pa tàbí tí wọn ò nílé mọ́. Bí ojú ọjọ́ ṣe rí yìí mú kó ṣòro láti rí àwọn tó fara pa níbi tí wọ́n há sí.”​—Reuters, February 6, 2023.

 Irú àwọn ìròyìn yìí máa ń bà wá nínú jẹ́ gan-an. Ọ̀dọ̀ Jèhófà “Ọlọ́run ìtùnú gbogbo” la ti lè rí ìrànlọ́wọ́ lásìkò tí àjálù bí èyí bá ṣẹlẹ̀. (2 Kọ́ríńtì 1:3) Ó ń jẹ́ ‘ká lè ní ìrètí nípasẹ̀ ìtùnú látinú Ìwé Mímọ́.’​—Róòmù 15:4.

 Bíbélì jẹ́ ká mọ:

  •   Àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìmìtìtì ilẹ̀.

  •   Ẹni tó lè tù wá nínú, táá sì fún wa nírètí.

  •   Bí Ọlọ́run ṣe máa fòpin sí ìyà.

 Tó o bá fẹ́ mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa àwọn kókó yìí, ka àwọn àpilẹ̀kọ yìí:

a Jèhófà ni orúkọ Ọlọ́run.​—Sáàmù 83:18.