Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Surasak Suwanmake/Moment via Getty Images

Ẹ MÁA ṢỌ́NÀ!

Ooru Tó Gbóná Janjan Mú Kárí Ayé Lọ́dún 2023​—Kí Ni Bíbélì Sọ?

Ooru Tó Gbóná Janjan Mú Kárí Ayé Lọ́dún 2023​—Kí Ni Bíbélì Sọ?

 Nítorí ojú ọjọ́ tí kò bára dé, ibi gbogbo láyé ni ooru tó gbóná janjan àtàwọn àjálù míì ti ooru ń fà ti ń han àwọn èèyàn léèmọ̀. Ẹ kíyè si àwọn ìròyìn tó tẹ̀ lé e yìí:

  •   “Láti nǹkan bí ọgọ́rùn-ún ọdún ó lé mẹ́rìnléláàádọ́rin (174) tí wọ́n ti ń ṣe àkọsílẹ̀ bí ojú ọjó ṣe ń móoru tó, ti oṣù June ọdún yìí ló tíì le jù.”​—National Oceanic and Atmospheric Administration, U.S. Department of Commerce, July 13, 2023.

  •   “Ooru tó gbóná janjan ń mú láwọn orílẹ̀-èdè bí Ítálì, Sípéènì, Faransé, Jámánì àti Poland, ó sì ṣeé ṣe káwọn erékùṣù tó wà ní Sicily àti Sardinia ní ojú ọjọ́ tó gbóná tó nǹkan bí 48°C [118°F.] Tí wọ́n bá fi ìwọ̀n yìí sórí nǹkan tí wọ́n fi ń díwọ̀n ooru, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé òhun ni ojú ọjọ́ tó tíì gbóná jù lọ nílẹ̀ Yúróòpù.”​—European Space Agency, July 13, 2023.

  •   “Bí ojú ọjọ́ ṣe túbọ̀ ń gbóná sí i yìí, ó ṣeé ṣe kí òjò àrọ̀ọ̀rọ̀dá tó sì máa jẹ́ léraléra pọ̀ gan-an, èyí sì lè fa àkúnya omi tó burú gan-an.”​—ọ̀gbéni Stefan Uhlenbrook, tó jẹ́ adarí ẹ̀ka hydrology, water and cryosphere ní World Meteorological Organization, July 17, 2023.

 Ṣé ìròyìn lemọ́lemọ́ nipa ojú ọjọ́ tó ń gbóná gan-an yìí kàn ẹ́? Jẹ́ ká wo ohun tí Bíbélì sọ nipa kókó yìí.

Ṣé ojú ọjọ́ tó ń gbóná yìí bá àṣọtẹ́lẹ̀ Bíbélì mu?

 Bẹ́ẹ̀ni. Ooru tó ń mú gan-an àtàwọn ìṣòro míì tí ojú ọjọ́ tí ò dáa ń fà kárí ayé bá ohun tí Bíbélì sọ pé á máa ṣẹlẹ̀ lákòókò wa yìí mu. Bí àpẹẹrẹ, Jésù sọ tẹ́lẹ̀ pé a máa rí “àwọn ohun tó ń bani lẹ́rù,” tàbí “ohun ẹ̀rù.” (Lúùkù 21:11; Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní) Bí ojú ọjọ́ ṣe túbọ̀ ń gbóná janjan kárí ayé ń mú kẹ́rù máa ba ọ̀pọ̀ pé, àwọn èèyàn máa tó ba ayé yìí jẹ́ débi tí ò fi ní ṣeé gbé mọ́.

Ṣé ìgbà kan ń bọ̀ tí ayé yìí ò ní ṣeé gbé mọ́?

 Rárá. Ọlọ́run dá ayé yìí ká lè máa gbé inú rẹ̀ títí láé; kò sì ní gbà káwọn èèyàn pa á run. (Sáàmù 115:16; Oníwàásù 1:4) Kódà, ó sọ pé òun máa “run àwọn tó ń run ayé.”​—Ìfihàn 11:18.

 Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé Ọlọ́run kò ní jẹ́ káwọ́n àjálù tó ń ṣẹlẹ̀ ba ayé yìí jẹ́.

  •   “[Ọlọ́run] mú kí ìjì náà rọlẹ̀, Ìgbì òkun sì pa rọ́rọ́.” (Sáàmù 107:29) Ọlọ́run lágbára láti kápá àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àdáyébá. Ó sì máa fòpin sí àwọn ìṣòro tí ojú ọjọ́ tí ò bára dé máa ń fà fún aráyé.

  •   “Ò ń bójú tó ayé, O mú kí ó ní ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ èso, kí ilẹ̀ rẹ̀ sì lọ́ràá dáadáa.” (Sáàmù 65:9) Ọlọ́run máa lo agbára ẹ̀ láti sọ ayé yìí di párádíse.

 Tó o bá fẹ́ mọ sì í nípa ohun tí Bíbélì sọ lórí bí Ọlọ́run ṣe máa tún ayé yìí ṣe, wo àpilẹ̀kọ náà “Ta Ló Máa Tún Ayé Yìí Ṣe?