ORIN 90
Ẹ Máa Gba Ara Yín Níyànjú
-
1. Bá a ṣe ńkóra jọ láti jọ́sìn,
Tí à ń fòótọ́ inú sin Jáà,
À ń ru àwọn ará wa sókè;
Sífẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ rere.
Ibi ààbò ni ìjọ wa jẹ́,
Ọkàn wa máa ń balẹ̀ níbẹ̀.
Àlàáfíà wà láàárín gbogbo wa,
A nífẹ̀ẹ́ ara wa dénú.
-
2. Ọ̀rọ̀ tá a sọ lákòókò tó yẹ
Máa ń tura, ó sì ńgbéni ró!
Ó máa ń jẹ́ káwọn tó sorí kọ́
Rítùnú, kí wọ́n sì láyọ̀.
Bí a ṣe jọ ń ṣiṣẹ́ níṣọ̀kan,
À ń wọ̀nà fún ayé tuntun!
À ń gbéra wa ró, a sì ńlókun;
A tún ń dúró ti ara wa.
-
3. Ọjọ́ Jèhófà ti sún mọ́lé.
Ojú ìgbàgbọ́ la fi ń rí i.
Torí náà, a ó máa pé jọ déédéé
Ká lè máa rìn lọ́nà ìyè.
Títí láé la ó máa sin Jèhófà,
Àwa àti ẹgbẹ́ ará.
Torí náà, ká máa gbéra wa ró
Ká lè jẹ́ adúróṣinṣin.
(Tún wo Lúùkù 22:32; Ìṣe 14: 21, 22; Gál. 6:2; 1 Tẹs. 5:14.)