Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orin 154

A Ó Máa Fara Dà Á Nìṣó

A Ó Máa Fara Dà Á Nìṣó

Wà á jáde:

(Mátíù 24:13)

  1. Bí ‘ṣòro bá dé

    Báwo la ṣe lè fara dàá?

    Jésù náà jìyà

    Àmọ́ ìrètí fúnun láyọ̀.

    Ìlérí, ìdájọ́

    Baba ló ńronú lé.

    (ÈGBÈ)

    Ó yẹ ká máa fara dàá.

    Ká gbèjà ìgbàgbọ́.

    Ìfẹ́ rẹ̀ sí wa dájú.

    A ó máa fara dàá títí dé òpin.

  2. Ó lè ti pẹ́ gan-an

    Táa ti ńdojú kọ ìṣòro;

    Báa tilẹ̀ ńsunkún,

    À ńr’ọ́jọ́ ‘wájú aláyọ̀.

    Táó máa gbé láìséwu,

    Aó máa fara dà á lọ.

    (Ègbè)

    Ó yẹ ká máa fara dàá.

    Ká gbèjà ìgbàgbọ́.

    Ìfẹ́ rẹ̀ sí wa dájú.

    A ó máa fara dàá títí dé òpin.

  3. A kò ní yẹsẹ̀

    Aò bẹ̀rù, kò síyè méjì.

    Aó máa fòótọ́ sìn

    Títí di ọjọ́ Jèhófà.

    Ká máa fara dàá lọ.

    Ọjọ́ náà ti dé tán.

    (Ègbè)

    Ó yẹ ká máa fara dàá.

    Ká gbèjà ìgbàgbọ́.

    Ìfẹ́ rẹ̀ sí wa dájú.

    A ó máa fara dàá títí dé òpin.