FEBRUARY 6, 2019
RỌ́ṢÍÀ
Ilé Ẹjọ́ ní Rọ́ṣíà Dá Dennis Christensen Lẹ́bi, Wọ́n sì Rán An Lẹ́wọ̀n Ọdún Mẹ́fà
Ní February 6, 2019, ilé ẹjọ́ kan lórílẹ̀-èdè Rọ́ṣíà dá Dennis Christensen lẹ́bi pé ó “ń ṣètò iṣẹ́ àjọ àwọn agbawèrèmẹ́sìn.” Wọ́n sì rán an lẹ́wọ̀n ọdún mẹ́fà. Àwọn oníròyìn láwọn ilẹ̀ míì ti sọ̀rọ̀ nípa ẹjọ́ tí kò tọ́ yìí, a sì máa pe ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn.
A ò ní dákẹ́ àdúrà fún Dennis Christensen àti ìyàwó rẹ̀, Irina pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ará wa ní Rọ́ṣíà bí wọ́n ṣe ‘fara balẹ̀, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀ lé’ Jèhófà.—Àìsáyà 30:15.