MAY 28, 2019
MOZAMBIQUE
Ìjì Líle Kenneth Jà ní Àríwá Mòsáńbíìkì
Ní April 25, 2019, ìjì líle kan tí wọ́n pè ní Kenneth jà ní àríwá orílẹ̀-èdè Mòsáńbíìkì. Ìgbà kejì nìyí tí ìjì líle tún jà léyìn Ìjì Líle Idai tó jà lóṣù March lórílẹ̀-èdè náà. Ìjì tó jà kẹ́yìn yìí fa omíyalé tó pọ̀, ó ba ọ̀pọ̀ ilé àti ọ̀nà jẹ́, kódà ńṣe ló mú kí nǹkan túbọ̀ nira lágbègbè tó ti jà.
Nǹkan bíi ọgọ́rùn-ún mẹ́ta (300) akéde ló ń gbé ní agbègbè Cabo Delgado, àmọ́ kò sí ìkankan lára wọn tí ìjì líle náà ṣe lẹ́se tàbí tó pa. Síbẹ̀, ìjì náà ba mẹ́sàn-án lára ilé àwọn ará wa jẹ́ kọjá àtúnṣe, ó sì tún ba ilé mẹ́rìndínlógún (16) míì jẹ́ díẹ̀. Yàtọ̀ síyẹn, ó ba Gbọ̀ngàn Ìjọba kan jẹ́ pátápátá, ó sì tún ba mẹ́ta míì jẹ́ díẹ̀. Alábòójútó àyíká tó wà lágbègbè náà àti aṣojú kan láti Ẹ̀ka Tó Ń Yàwòrán Ilé Tó sì Ń Kọ́ Ọ pẹ̀lú arákùnrin méjì láti ọ́fíìsì àwọn atúmọ̀ èdè lọ sọ́dọ̀ gbogbo àwọn ìjọ tí àjálù náà kàn, wọ́n sì fún wọn ní ìṣírí.
À ń rántí àwọn ará wa yìí nínú àdúrà bí wọ́n ṣe ń wojú Jèhófà, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀ lé e pé kó fún wọn lókun, kó sì ràn wọ́n lọ́wọ́ “ní àkókò wàhálà.”—Sáàmù 46:1.