Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Ilé ìdílé Ẹlẹ́rìí kan tí iná jó kanlẹ̀

APRIL 25, 2019
SOUTH KOREA

Iná Ńlá Sọ Nínú Igbó Létí Ìlà Oòrùn South Korea

Iná Ńlá Sọ Nínú Igbó Létí Ìlà Oòrùn South Korea

Ní April 4, 2019, iná ńlá kan sọ létí ìlà oòrùn orílẹ̀-èdè South Korea ní agbègbè tí wọ́n ń pè ní Gangwon Province. Kò pẹ́ rárá tí iná náà fi ràn, èyí sì mú kí ìjọba kéde pé wàhálà ti wọ̀lú káàkiri orílẹ̀-èdè náà. Kí wọ́n tó lè kápá iná náà, ó ti jó ẹgbẹ̀rún mẹ́rin (4,000) eékà ilẹ̀, ó sì ti pa èèyàn méjì.

Ẹ̀ka ọ́fíìsì wa ròyìn pé kò sí ìkankan lára àwọn ará wa tó kú. Àmọ́ iná náà jó ilé mẹ́jọ tí àwọn ará wa mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n (27) ń gbé. Ẹ̀ka ọ́fíìsì dá Ìgbìmọ̀ Tó Ń Ṣètò Ìrànwọ́ Nígbà Àjálù sílẹ̀, àwọn alábòójútó àyíká tó wà lágbègbè náà àtàwọn alàgbà ìjọ ń fáwọn tí àjàlù yìí kàn níṣìírí, wọ́n sì ń pèsè ohun tí wọ́n nílò fún wọn.

Ó dá wa lójú pé Jèhófà máa jẹ́ ‘ibi ààbò àti okun pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ tó wà lárọ̀ọ́wọ́tó ní àkókò wàhálà’ fáwọn ará wa yìí.—Sáàmù 46:1.